< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
God, you are the one whom I praise, [So please] answer [my prayer],
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
because wicked people slander me and tell [MTY] lies about me.
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
They are constantly saying that they hate me, and they say evil things about me for no reason.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
I show them that I want to be their friends and I pray for them, but [instead of being kind to me], they say that I have done evil things.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
In return for my doing good things for them and loving them, they do evil things to me and hate me.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
They said, “Appoint a wicked [judge] who will judge him, and bring in one of his enemies who will stand up and accuse him.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
And cause that when the trial [ends], [the judge will] declare that he is guilty, and that [even] his prayer will be considered to be a sin.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
[Then], cause that he will soon die and that someone else will have his job/work (OR, possessions).
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Cause that his children will not have a father any more and that his wife will become a widow.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Cause that his children will be forced to leave the ruined homes that they have been living in and wander around begging for food.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Cause that all the people to whom he owed money will seize all his property; Cause that strangers will take away everything that he worked to acquire.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Cause that [while he is still living] no one will be kind to him, and [after he dies], cause that no one will pity his children.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Cause that all his descendants will die and that his grandchildren will not remember who he [MTY] was.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Yahweh, remember [and do not forgive] his ancestors for the evil things that they did, and do not [even] forgive the sins that his mother committed;
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
think about his sins continually, and cause that his name will be completely forgotten.
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
He never was kind to anyone; he (persecuted/cause problems for) poor and needy [people] and even killed helpless [people].
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
He liked to curse [people]. [So] cause those terrible things that he requested to happen to others to happen to him! He did not want to bless [others], [so] cause that no one will bless him!
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
He cursed other people [as often/easily] as he put on his clothes [SIM]; cause that the terrible things that he wanted to happen to others will [happen to him and] enter his body like water [that he drinks] [SIM], like [olive] oil soaks into a person’s bones [when it is rubbed on his skin] [SIM].
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Cause that those terrible things will cling to him like his clothes and be around him like the belt that he wears every day.”
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Yahweh, I want you to punish all my enemies that way, those who say evil things about me.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
But Yahweh, my God, do good things for me in order that I may honor you; rescue me [from my enemies] because your faithfully loving me is good.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
[I ask you to do this] because I am poor and needy and my inner being is (full of pain/very troubled/discouraged).
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
[I think that] my time [to remain alive] is short, like an evening shadow [that will soon disappear] [SIM]. I will be blown away like a locust/grasshopper is blown [by the wind].
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
My knees are weak because I have (fasted/abstained from eating food) very often, and my body has become very thin.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
The people who accuse me make fun of me; when they see me, they [insult me by] shaking their heads [at me as though I were an evil man].
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Yahweh, my God, help me! Because you faithfully love [me], rescue me!
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
[When you save me], cause my enemies to know that you are the one who has done it!
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
They may curse me, but I ask that you bless me. Cause those who (persecute/cause problems for) me [to be defeated and as a result] to be disgraced/ashamed, and cause me to be glad/happy!
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Cause those who accuse me to be completely disgraced; cause [other people to see] that they are disgraced, as [easily as they see] the clothes that they wear [SIM]!
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
But I will thank Yahweh very greatly; I will praise him [when I am] among the crowd [of people who are worshiping him].
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
[I will do that] because he defends [MTY] needy [people like me], and saves us from those who have decided/declared that we must be executed.

< Psalms 109 >