< Psalms 108 >

1 Orin. Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
Cantique de psaume, de David lui-même. Mon cœur est prêt, ô Dieu, mon cœur est prêt, je chanterai, je jouerai du psaltérion au milieu de ma gloire.
2 Jí ohun èlò orin àti haapu! Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
Lève-toi, ô ma gloire, lève-toi, psaltérion, et toi, harpe: je me lèverai au point du jour.
3 èmi ó yìn ọ́, Olúwa, nínú àwọn orílẹ̀-èdè, èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
Je vous louerai parmi les peuples. Seigneur, et je dirai un psaume en votre honneur parmi les nations.
4 Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ ju àwọn ọ̀run lọ àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
Parce que votre miséricorde est grande au-dessus des cieux, et que votre vérité s’élève jusqu’aux nues.
5 Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run, àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
Soyez exalté au-dessus des cieux, ô Dieu, et que sur toute la terre éclate votre gloire,
6 Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là; fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà, kí o sì dá mi lóhùn
Afin que vos bien-aimés soient délivrés. Sauvez-moi par votre droite, et exaucez-moi;
7 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu, èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
Dieu a parlé dans son sanctuaire:
8 Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi, Efraimu ni ìbòrí mi, Juda ni olófin mi,
À moi est Galaad, et à moi est Manassé; Ephraïm est l’appui de ma tête.
9 Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí, lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
Moab est le vase de mon espérance.
10 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi? Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
Qui me conduira dans une ville fortifiée? qui me conduira jusque dans l’Idumée?
11 Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀. Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
Ne sera-ce pas vous, ô Dieu, qui nous avez rejetés? et ne sortirez-vous point, ô Dieu, à la tête de nos armées?
12 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú, nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
Donnez-nous du secours, pour nous tirer de la tribulation, parce que vain est le salut de l’homme.
13 Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
En Dieu nous ferons preuve de valeur, et lui-même réduira au néant nos ennemis.

< Psalms 108 >