< Psalms 107 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Ah, Perwerdigargha teshekkür éytinglar! Chünki U méhribandur, ebediydur Uning méhir-muhebbiti!
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Perwerdigar yaw qolidin qutquzghanlar, U hemjemet bolup qutquzghan xelqi buni dawamliq bayan qilsun —
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Yeni U sherq bilen gherbtin, shimal bilen jenubtin, Herqaysi yurtlardin yighiwélin’ghanlar buni éytsun!
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Ular chöl-bayawanni kézip pinhan yolda adashti, Adem makanlashqan héchbir sheherni tapalmastin.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Ach hemde ussuz bolup, Jéni chiqay dep qaldi.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Andin Perwerdigargha peryad qildi, U ularni musheqqetliridin azad qildi.
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Makanlashqudek sheherge yetküche, U ularni tüz yolda bashlidi.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Ular Perwerdigargha teshekkür éytsun! Uning özgermes muhebbiti üchün, Insan balilirigha körsetken möjiziliri üchün!
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
Chünki U changqighan köngülni qandurdi, Ach qalghan janni ésil németler bilen toldurdi.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Zülmette, ölüm kölenggiside yashighanlar, Tömür kishen sélinip, azab chekkenlerni bolsa,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
(Chünki ular Tengrining emirlirige qarshiliq qildi, Hemmidin Aliy Bolghuchining nesihetini kemsitti)
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
— U ularni japa-musheqqet tartquzup kemter qildi, Ular putliship yiqildi, ulargha yardemge birsimu yoq idi.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Andin Perwerdigargha yélinip peryad qildi, U ularni musheqqetliridin azad qildi.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Ularni zulmet hem ölüm sayisidin chiqirip, Ularning zenjir-asaretlirini sundurup tashlidi.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Ular Perwerdigargha teshekkür éytsun! Uning özgermes muhebbiti üchün, Insan balilirigha körsetken möjiziliri üchün!
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Mana U mis derwazilarni pare-pare qilip, Tömür taqaqlarni késip tashlidi.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Hamaqetler öz itaetsizlik yolliridin, Qebihlikliridin azablargha uchraydu;
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Könglide herxil ozuq-tülüktin bizar bolup, Ölüm derwazilirigha yéqinlishidu.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Andin Perwerdigargha yélinip peryad qilidu, U ularni musheqqetliridin azad qilidu.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
U söz-kalamini ewetip, ularni saqaytidu, Ularni zawalliqliridin qutquzidu.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Ular Perwerdigargha teshekkür éytsun! Uning özgermes muhebbiti üchün, Adem balilirigha körsetken möjiziliri üchün!
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
Qurbanliq süpitide teshekkürler éytsun, Uning qilghanlirini tentenilik naxshilar bilen bayan qilsun!
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Kémilerde déngizgha chüshüp qatnighuchilar, Ulugh sularda tirikchilik qilghuchilar,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Bular Perwerdigarning ishlirigha guwahchidur, Chongqur okyanda körsetken karametlerni körgüchidur.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Chünki U bir söz bilenla shiddetlik shamalni chiqirip, Dolqunlirini örkeshlitidu;
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Kémichiler asman-pelek örleydu, Sularning tehtilirige chüshidu, Dehshettin ularning jéni érip kétidu.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Ular mest ademdek eleng-seleng irghanglaydu, Herqandaq eqil-charisi tügeydu;
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Andin Perwerdigargha yélinip peryad qilidu, U ularni musheqqetliridin azad qilidu.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
U boranni tinchitidu, Su dolqunlirimu jim bolidu.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Shuning bilen ular tinchliqidin shadlinidu; U ularni teshna bolghan aramgahigha yéteklep baridu.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Ular Perwerdigargha teshekkür éytsun! Uning özgermes muhebbiti üchün, Insan balilirigha körsetken möjiziliri üchün!
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Ular xelqning jamaitidimu Uni ulughlisun, Aqsaqallar mejliside Uni medhiyilisun.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
U deryalarni chölge, Bulaqlarni qaqasliqqa aylanduridu.
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
Ahalisining yamanliqi tüpeylidin, Hosulluq yerni shorluq qilidu.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
U yene chöl-bayawanni kölge, Changqaq yerni bulaqlargha aylanduridu;
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Achlarni shu yerge jaylashturup, Ular olturaqlashqan bir sheherni berpa qilidu;
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Ular étizlarni heydep-térip, üzümzarlarni berpa qilidu; Bular hosul-mehsulatni mol béridu.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
U ulargha beriket béridu, Shuning bilen ularning sani xélila éship baridu, U ularning mal-waranlirini héch azaytmaydu.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Ular yene jebir-zulum, bala-qaza hem derd-elemge yoluqup, Sani aziyip, pükülidu.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
U ésilzadiler üstige kemsitishlirini tökidu, Yolsiz desht-sehrada ularni sergerdan qilidu;
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
Lékin miskin ademni jebir-zulumdin yuqiri kötürüp saqlaydu, Uning aile-tawabatini qoy padisidek köp qilidu.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Buni köngli duruslar körüp shadlinidu; Pasiqlarning aghzi étilidu.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Kimki dana bolsa, bularni bayqisun, Perwerdigarning méhir-shepqetlirini chüshensun!

< Psalms 107 >