< Psalms 107 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Tacken HERREN, ty han är god, ty hans nåd varar evinnerligen.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Så säge HERRENS förlossade, de som han har förlossat ur nöden,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
de som han har församlat ifrån länderna, från öster och från väster, från norr och från havssidan.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
De irrade omkring i öknen på öde stigar, de funno ingen stad där de kunde bo;
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
de hungrade och törstade, deras själ försmäktade i dem.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Men de ropade till HERREN i sin nöd, och han räddade dem ur deras trångmål.
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Och han ledde dem på en rätt väg, så att de kommo till en stad där de kunde bo.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
De må tacka HERREN för hans nåd och för hans under med människors barn,
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
att han mättade den försmäktande själen och uppfyllde den hungrande själen med sitt goda.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
De sutto i mörker och dödsskugga, fångna i elände och järnbojor,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
därför att de hade varit gensträviga mot Guds ord och hade föraktat den Högstes råd.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Han kuvade deras hjärtan med olycka; de kommo på fall och hade ingen hjälpare.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Men de ropade till HERREN i sin nöd, och han frälste dem ur deras trångmål;
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
han förde dem ut ur mörkret och dödsskuggan, och deras bojor slet han sönder.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
De må tacka HERREN för hans nåd och för hans under med människors barn,
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
att han krossade kopparportarna och bröt sönder järnbommarna.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
De voro oförnuftiga, ty de vandrade i överträdelse, och blevo nu plågade för sina missgärningars skull;
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
deras själ vämjdes vid all mat, och de voro nära dödens portar.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Men de ropade till HERREN i sin nöd, och han frälste dem ur deras trångmål.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Han sände sitt ord och botade dem och räddade dem från graven.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
De må tacka HERREN för hans nåd och för hans under med människors barn;
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
de må offra lovets offer och förtälja hans verk med jubel.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
De foro på havet med skepp och drevo sin handel på stora vatten;
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
där fingo de se HERRENS gärningar och hans under på havsdjupet.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Med sitt ord uppväckte han stormvinden, så att den hävde upp dess böljor.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
De foro upp mot himmelen, ned i djupen; deras själ upplöstes av ångest.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
De raglade och stapplade såsom druckna, och all deras vishet blev till intet.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Men de ropade till HERREN i sin nöd, och han förde dem ut ur deras trångmål.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Han förbytte stormen i lugn, så att böljorna omkring dem tystnade.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Och de blevo glada att det vart stilla, och han förde dem till den hamn dit de ville.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
De må tacka HERREN för hans nåd och för hans under med människors barn;
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
de må upphöja honom i folkets församling och lova honom där de äldste sitta.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
Han gjorde strömmar till öken, källsprång till torr mark,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
bördigt land till salthed, för dess inbyggares ondskas skull.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Han gjorde öknen till en vattenrik sjö och torrt land till källsprång.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Och han lät de hungrande bo där, och de byggde en stad där de kunde bo.
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
De besådde åkrar och planterade vingårdar, som gåvo dem sin frukt i avkastning.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Han välsignade dem, och de förökades storligen, och deras boskapshjordar lät han icke förminskas.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Väl blevo de sedan ringa och nedböjda, i det olycka och bedrövelse tryckte dem,
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
men han som utgjuter förakt över furstar och låter dem irra omkring i väglösa ödemarker,
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
han upphöjde då den fattige ur eländet och lät släkterna växa till såsom fårhjordar.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
De redliga se det och glädja sig, och all orättfärdighet måste tillsluta sin mun.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Den som är vis, han akte härpå och besinne HERRENS nådegärningar.