< Psalms 107 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
ALABAD á Jehová, porque es bueno; porque para siempre [es] su misericordia.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Dígan[lo] los redimidos de Jehová, los que ha redimido del poder del enemigo,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Y los ha congregado de las tierras, del oriente y del occidente, del aquilón y de la mar.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Anduvieron perdidos por el desierto, por la soledad sin camino, no hallando ciudad de población.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Hambrientos y sedientos, su alma desfallecía en ellos.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Habiendo empero clamado á Jehová en su angustia, librólos de sus aflicciones:
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Y dirigiólos por camino derecho, para que viniesen á ciudad de población.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Alaben la misericordia de Jehová, y sus maravillas para con los hijos de los hombres.
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
Porque sació al alma menesterosa, y llenó de bien al alma hambrienta.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Los que moraban en tinieblas y sombra de muerte, aprisionados en aflicción y en hierros;
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
Por cuanto fueron rebeldes á las palabras de Jehová, y aborrecieron el consejo del Altísimo,
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Por lo que quebrantó él con trabajo sus corazones, cayeron y no hubo quien [les] ayudase;
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Luego que clamaron á Jehová en su angustia, librólos de sus aflicciones.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Sacólos de las tinieblas y de la sombra de muerte, y rompió sus prisiones.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Alaben la misericordia de Jehová, y sus maravillas para con los hijos de los hombres.
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Porque quebrantó las puertas de bronce, y desmenuzó los cerrojos de hierro.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Los insensatos, á causa del camino de su rebelión y á causa de sus maldades, fueron afligidos.
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Su alma abominó toda vianda, y llegaron hasta las puertas de la muerte.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Mas clamaron á Jehová en su angustia, y salvólos de sus aflicciones.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Envió su palabra, y curólos, y librólos de su ruina.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Alaben la misericordia de Jehová, y sus maravillas para con los hijos de los hombres:
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
Y sacrifiquen sacrificios de alabanza, y publiquen sus obras con júbilo.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Los que descienden á la mar en navíos, y hacen negocio en las muchas aguas,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Ellos han visto las obras de Jehová, y sus maravillas en el profundo.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
El dijo, é hizo saltar el viento de la tempestad, que levanta sus ondas.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Suben á los cielos, descienden á los abismos: sus almas se derriten con el mal.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Tiemblan, y titubean como borrachos, y toda su ciencia es perdida.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Claman empero á Jehová en su angustia, y líbralos de sus aflicciones.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Hace parar la tempestad en sosiego, y se apaciguan sus ondas.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Alégranse luego porque se reposaron; y él los guía al puerto que deseaban.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Alaben la misericordia de Jehová, y sus maravillas para con los hijos de los hombres.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Y ensálcenlo en la congregación del pueblo; y en consistorio de ancianos lo alaben.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
El vuelve los ríos en desierto, y los manantiales de las aguas en secadales;
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
La tierra fructífera en salados, por la maldad de los que la habitan.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Vuelve el desierto en estanques de aguas, y la tierra seca en manantiales.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Y allí aposenta á los hambrientos, y disponen ciudad para habitación;
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Y siembran campos, y plantan viñas, y rinden crecido fruto.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Y los bendice, y se multiplican en gran manera; y no disminuye sus bestias.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Y luego son menoscabados y abatidos á causa de tiranía, de males y congojas.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
El derrama menosprecio sobre los príncipes, y les hace andar errados, vagabundos, sin camino:
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
Y levanta al pobre de la miseria, y hace [multiplicar] las familias como [rebaños de] ovejas.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Vean los rectos, y alégrense; y toda maldad cierre su boca.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
¿Quién es sabio y guardará estas cosas, y entenderá las misericordias de Jehová?