< Psalms 107 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Cookeriai Jehova ngaatho, nĩgũkorwo nĩ mwega; wendo wake ũtũũraga tene na tene.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Andũ arĩa makũũrĩtwo nĩ Jehova nĩmakiuge ũguo: o acio akũũrĩte kuuma guoko-inĩ gwa thũ,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
o acio aacookanĩrĩirie amarutĩte mabũrũri-inĩ, kuuma mwena wa irathĩro na wa ithũĩro, na kuuma mwena wa gathigathini na wa gũthini.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Amwe morũũrire werũ-inĩ ũtarĩ kĩndũ, maagĩte njĩra ya kũmakinyia itũũra inene kũrĩa mangĩatũũrire.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Maarĩ ahũtu na makanyoota, na makaaga mwĩhoko thĩinĩ wao.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Nao magĩkaĩra Jehova marĩ mĩnyamaro-inĩ, nake akĩmahonokia kuuma thĩĩna-inĩ.
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Aamagereirie njĩra nũngarũ, nginya magĩkinya itũũra inene kũrĩa mangĩonire gwa gũtũũra.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Nĩmagĩcookerie Jehova ngaatho nĩ ũndũ wa wendo wake ũrĩa ũtathiraga, na mawĩko make ma magegania marĩa eekĩire andũ,
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
nĩgũkorwo nĩwe ũnyootoraga andũ arĩa anyootu, na akahũũnia arĩa ahũtu na maũndũ mega.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Amwe maaikarĩte nduma-inĩ o na nduma-inĩ nene mũno, makĩnyamarĩka marĩ ohe na mĩnyororo ya kĩgera,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
nĩgũkorwo nĩmaremeire ciugo cia Mũrungu, o na makĩagĩra kĩrĩra kĩa Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno bata.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Nĩ ũndũ ũcio akĩmarutithia wĩra wa hinya; nao makĩhĩngwo na gũkĩaga wa kũmateithia.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Hĩndĩ ĩyo magĩkaĩra Jehova marĩ thĩĩna-inĩ, nake akĩmahonokia kuuma mĩnyamaro-inĩ.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Nake aamarutire nduma-inĩ, akĩmaruta kũu nduma-inĩ nene mũno, na agĩtuanga mĩnyororo ĩrĩa moohetwo nayo.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Nĩmagĩcookerie Jehova ngaatho nĩ ũndũ wa wendo wake ũrĩa ũtathiraga, na mawĩko make ma magegania marĩa eekĩire andũ,
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
nĩgũkorwo nĩoinangaga ihingo cia gĩcango na akoinanga mĩgĩĩko ya kĩgera.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Amwe maatuĩkire andũ akĩĩgu nĩ ũndũ wa mĩthiĩre yao ya ũremi, o na nĩ ũndũ wa waganu wao magĩtuĩka a gũthĩĩnĩka.
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Magĩtuĩka a kũira ngoro mona irio o ciothe, nao magĩkuhĩrĩria ihingo cia gĩkuũ.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Hĩndĩ ĩyo magĩkaĩra Jehova marĩ mĩnyamaro-inĩ, nake akĩmaruta thĩĩna-inĩ.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Aatũmire kiugo gĩake akĩmahonia; aamateithũrire kuuma mbĩrĩra-inĩ.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Nĩmagĩcookerie Jehova ngaatho nĩ ũndũ wa wendo wake ũrĩa ũtathiraga, na mawĩko make ma magegania marĩa eekĩire andũ.
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
Nĩmakĩrute igongona rĩa gũcookia ngaatho, na mamenyithanie mawĩko make makĩinaga nyĩmbo cia gĩkeno.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Angĩ maagereire iria-inĩ marĩ marikabu-inĩ; maathiiaga wonjoria kũu maria-inĩ manene.
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Nĩmoonire mawĩko ma Jehova, makĩona ciĩko ciake cia magegania kũu kũriku.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Nĩgũkorwo aaririe, akĩarahũra kĩhuhũkanio kĩrĩa gĩatũmire iria rĩgĩe na makũmbĩ.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Marikabu igĩikanio na igũrũ, na igĩcooka igĩikanio na kũu thĩ kũrĩa kũriku; andũ acio magĩkua ngoro nĩ ũndũ marĩ ũgwati-inĩ mũnene.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Makĩagaga na magĩtũgũũga ta andũ arĩĩu; ũũgĩ wao wothe nĩwakinyĩte mũthia.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Hĩndĩ ĩyo magĩkaĩra Jehova marĩ thĩĩna-inĩ, nake akĩmahonokia kuuma mĩnyamaro-inĩ.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Nake akĩhooreria kĩhuhũkanio kĩu kĩnene; namo makũmbĩ ma iria rĩu magĩkirio ki.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Nao magĩkena nĩ iria rĩu kũhoorera, nake akĩmakinyia nginya gĩcukĩro-inĩ kĩa marikabu kĩrĩa merirĩirie gũkinya.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Nĩmagĩcookerie Jehova ngaatho nĩ ũndũ wa wendo wake ũrĩa ũtathiraga, na mawĩko make ma magegania marĩa eekĩire andũ.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Nĩmamũtũũgĩrie kĩũngano-inĩ kĩa andũ, na mamũgooce marĩ kĩama-inĩ kĩa athuuri.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
Aagarũrire kũrĩa kwarĩ njũũĩ gũgĩtuĩka werũ, nakuo kũrĩa kwarĩ ithima ciathereraga gũgĩtuĩka kũndũ kũngʼaru,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
naguo bũrũri ũrĩa woimaga irio mũno akĩũtua werũ wa igata ũtaarĩ kĩndũ, tondũ wa waganu wa andũ arĩa maatũũraga kuo.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Aagarũrire kũrĩa kwarĩ werũ gũkĩgĩa tũria twa maaĩ, nakuo kũrĩa kwarĩ kũngʼaru agĩtũma gũkunũke ithima;
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
nao andũ arĩa maarĩ ahũtu akĩmarehe kuo, nao magĩaka itũũra inene rĩa gũikara.
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Maarĩmire mĩgũnda na makĩhaanda mĩthabibũ, ĩrĩa yaciarire magetha maingĩ;
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
aamarathimire nao makĩingĩha mũno, na ndaarekire mahiũ mao manyiihe.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Mũigana wao ũgĩcooka ũkĩnyiiha, na makĩagithio hinya, nĩ kũhinyĩrĩrio, na kũnyariirĩka, o na kĩeha;
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
we ũrĩa ũnyararithagia andũ arĩa marĩ igweta-rĩ, agĩtũma morũũre kũndũ gũtaarĩ njĩra.
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
No rĩrĩ, nĩarutire andũ arĩa abatari mathĩĩna-inĩ, na andũ a nyũmba ciao akĩmaingĩhia o ta mahiũ.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Andũ arĩa arũngĩrĩru monaga ũguo magakena, no arĩa othe aaganu nĩgũkirio makiragio.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Mũndũ o wothe mũũgĩ-rĩ, nĩarũmbũiye maũndũ macio, na ecũũranie ũhoro wa wendo mũnene wa Jehova.