< Psalms 107 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
“Danket Jahwe, denn er ist gütig, denn ewig währt seine Gnade!”
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
sollen die von Jahwe Erlösten sprechen, die er aus der Drangsal erlöst
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
und die er aus den Ländern gesammelt hat, vom Aufgang und vom Niedergang, von Norden und von Westen her.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Sie irrten in der Wüste, in wegloser Einöde; sie fanden keine Stadt, in der sie wohnen konnten,
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
waren hungrig und durstig; ihre Seele in ihnen verzagte.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Da schrieen sie zu Jahwe in ihrer Not; der errettete sie aus ihren Ängsten
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
und führte sie auf ebenem Wege, daß sie nach einer Stadt wanderten, in der sie wohnen konnten.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Sie mögen Jahwe für seine Gnade danken und für seine Wunder an den Menschenkindern,
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
daß er die lechzende Seele gesättigt und die hungernde Seele mit Gutem erfüllt hat.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Die in Finsternis und Umnachtung saßen, in Elend und Eisen gefangen, -
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
denn sie hatten den Worten Gottes widerstrebt und den Ratschluß des Höchsten verachtet;
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
und er beugte ihren Übermut durch Trübsal: sie sanken hin und niemand half.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Da schrieen sie zu Jahwe in ihrer Not; der half ihnen aus ihren Ängsten.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Er führte sie heraus aus der Finsternis und Umnachtung und zerriß ihre Bande.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Sie mögen Jahwe für seine Gnade danken und für seine Wunder an den Menschenkindern.
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Denn er zerbrach die ehernen Thüren und zerhieb die eisernen Riegel.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Die da hinsiechten infolge ihres sündigen Wandels und um ihrer Verschuldungen willen geplagt wurden;
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
jegliche Speise verabscheute ihre Seele, und sie waren schon nahe an den Thoren des Todes:
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Da schrieen sie zu Jahwe in ihrer Not; der half ihnen aus ihren Ängsten.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Er sandte sein Wort und heilte sie und ließ sie aus ihren Gruben entrinnen.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Sie mögen Jahwe für seine Gnade danken und für seine Wunder an den Menschenkindern
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
und mögen Dankopfer bringen und seine Werke mit Jubel erzählen.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Die auf Schiffen das Meer befuhren, auf großen Wassern Handel trieben,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
die haben die Werke Jahwes geschaut und seine Wunder in der Tiefe!
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Denn er gebot, da entstand ein Sturmwind; der hob seine Wellen hoch empor.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Sie stiegen zum Himmel auf, fuhren in die Tiefen hinab; ihre Seele verzagte in solcher Not.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Sie tanzten und schwankten wie ein Trunkener, und alle ihre Weisheit wurde zu nichte gemacht:
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Da schrieen sie zu Jahwe in ihrer Not; der befreite sie aus ihren Ängsten.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Er stillte den Sturm zum Säuseln, und es schwiegen ihre Wellen.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Da wurden sie froh, daß sie sich legten, und er führte sie zum ersehnten Hafen.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Sie mögen Jahwe für seine Gnade danken und für seine Wunder an den Menschenkindern
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
und mögen ihn in der Volksgemeinde erheben und im Rate der Vornehmen rühmen.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
Er machte Ströme zur Wüste und Quellorte von Gewässern zu dürrem Lande,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
fruchtbares Land zur salzigen Steppe wegen der Bosheit derer, die es bewohnten.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Er machte die Wüste zum Wasserteich und dürres Land zu Quellorten von Gewässern.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Er ließ daselbst Hungernde wohnen, und sie gründeten eine Stadt, in der sie wohnen konnten.
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Sie besäeten Felder und pflanzten Weinberge, die gaben alljährlich Früchte.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Und er segnete sie, daß sie sich überaus vermehrten, und gab ihnen nicht wenig Vieh.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Aber sie nahmen ab und wurden gebeugt durch den Druck des Unglücks und Jammers.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
“Er gießt Verachtung über Edle ausund läßt sie irren in unwegsamer Öde.”
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
Er hob den Armen aus dem Elend empor und machte die Geschlechter einer Herde gleich.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
“Die Frommen sehen's und freuen sich, und die Bosheit schließt ihr Maul”.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Wer ist weise? Der beachte dies, und sie mögen merken auf die Gnadenerweisungen Jahwes!

< Psalms 107 >