< Psalms 107 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Célébrez l'Éternel; car il est bon, Et sa miséricorde dure éternellement!
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Ainsi parleront les rachetés de l'Éternel, Ceux qu'il a rachetés de la main de l'oppresseur,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Et qu'il a rassemblés de tous les pays, De l'Orient et de l'Occident, du Nord et du Midi.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Ils erraient dans le désert, sur un chemin solitaire; Ils ne trouvaient aucune ville qui pût leur servir de refuge.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Ils étaient affamés et altérés; Leur âme défaillait en eux.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Alors ils ont crié vers l'Éternel, dans leur détresse, Et il les a délivrés de leurs angoisses.
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Il les a conduits par le droit chemin, Jusque dans une ville qu'ils ont habitée.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Qu'ils célèbrent donc la bonté de l'Éternel, Et ses miracles en faveur des enfants des hommes!
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
Car il a rassasié l'âme altérée. Et comblé de biens l'âme affamée.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
D'autres habitaient dans les ténèbres Et dans l'ombre de la mort; Ils étaient captifs et gémissaient dans les chaînes,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
Pour avoir été rebelles aux paroles de Dieu, Et avoir méprisé le conseil du Très-Haut.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Il avait humilié leur coeur par la souffrance: Ils succombaient, sans que personne ne les secourût.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Alors ils ont crié vers l'Éternel, dans leur détresse, Et il les a délivrés de leurs angoisses.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Il les a tirés des ténèbres et de l'ombre de la mort; Il a brisé leurs chaînes.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Qu'ils célèbrent donc la bonté de l'Éternel, Et ses miracles en faveur des enfants des hommes!
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Car il a brisé les portes d'airain, Et rompu les barreaux de fer.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Insensés qu'ils étaient! Ils portaient la peine De leurs transgressions et de leurs iniquités;
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Ils avaient en horreur toute nourriture; Ils touchaient aux portes de la mort.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Alors ils ont crié vers l'Éternel, dans leur détresse, Et il les a délivrés de leurs angoisses.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Il a envoyé sa parole; il les a guéris, Et il les a retirés de leurs tombeaux.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Qu'ils célèbrent donc la bonté de l'Éternel, Et ses miracles en faveur des enfants des hommes!
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
Qu'ils offrent des sacrifices d'actions de grâces Et racontent ses oeuvres avec des chants de triomphe!
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Ceux qui descendent sur la mer, dans des navires. Et qui trafiquent sur les grandes eaux,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Ceux-là voient les oeuvres de l'Éternel, Et ses merveilles dans les profondeurs de l'abîme.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Il parle, et il fait lever un vent de tempête, Qui soulève les vagues de la mer.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Ils montent aux cieux; ils descendent aux abîmes; Leur âme se fond d'angoisse.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Ils ensemencent des champs, et ils plantent des vignes, Qui portent des fruits abondants.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Alors ils ont crié vers l'Éternel, dans leur détresse, Et il les a délivrés de leurs angoisses.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Il fait succéder le calme à la tempête, Et les vagues s'apaisent.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Ils se réjouissent de ce qu'elles sont calmées. Et Dieu les conduit au port qu'ils désiraient.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Qu'ils célèbrent donc la bonté de l'Éternel, Et ses miracles en faveur des enfants des hommes!
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Qu'ils l'exaltent dans l'assemblée du peuple! Qu'ils le louent dans le conseil des anciens!
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
L'Éternel change les fleuves en désert, Les sources d'eau en un sol aride,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
Et la terre fertile en lande salée, A cause de la méchanceté de ses habitants.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Il change aussi le désert en étang, Et la terre aride en sources d'eau.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Il y fait habiter ceux qui étaient affamés: Ils fondent une ville pour y demeurer.
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Ils ensemencent des champs, et ils plantent des vignes, Qui portent des fruits abondants.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Dieu les bénit: ils deviennent très nombreux, Et il ne laisse pas diminuer leur bétail.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
D'autres sont amoindris et humiliés Par l'oppression, le malheur et la souffrance.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
L'Éternel répand le mépris sur les grands. Et les fait errer dans un désert sans route.
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
Mais il délivre de leur affliction les malheureux, Et rend leurs familles nombreuses Comme de grands troupeaux.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
A cette vue, les justes sont remplis de joie; Mais tous les injustes ont la bouche fermée.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Que celui qui est sage prenne garde à ces choses. Et qu'il sache comprendre les bontés de l'Éternel!

< Psalms 107 >