< Psalms 107 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Célébrez l’Éternel! Car il est bon; car sa bonté demeure à toujours.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Que les rachetés de l’Éternel le disent, ceux qu’il a rachetés de la main de l’oppresseur,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Et qu’il a rassemblés des pays, du levant et du couchant, du nord et de la mer.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Ils errèrent par le désert, dans un chemin solitaire; ils ne trouvèrent pas de ville pour y habiter;
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Ils étaient affamés et altérés, leur âme défaillait en eux.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Alors ils crièrent à l’Éternel dans leur détresse, [et] il les délivra de leurs angoisses,
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
Et les conduisit dans un chemin droit, pour aller dans une ville habitable.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Qu’ils célèbrent l’Éternel pour sa bonté, et pour ses merveilles envers les fils des hommes!
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
Car il a rassasié l’âme altérée, et a rempli de biens l’âme affamée.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Ceux qui habitent dans les ténèbres et dans l’ombre de la mort, liés d’affliction et de fers,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
Parce qu’ils se sont rebellés contre les paroles de Dieu, et ont méprisé le conseil du Très-haut…
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Et il a humilié leur cœur par le travail; ils ont trébuché, sans qu’il y ait personne qui les secoure.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Alors ils crièrent à l’Éternel dans leur détresse, [et] il les délivra de leurs angoisses:
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Il les fit sortir des ténèbres et de l’ombre de la mort, et rompit leurs liens.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Qu’ils célèbrent l’Éternel pour sa bonté, et pour ses merveilles envers les fils des hommes!
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Car il a brisé les portes d’airain, et a mis en pièces les barres de fer.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Les insensés, à cause de la voie de leur transgression, et à cause de leurs iniquités, sont affligés;
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Leur âme abhorre toute nourriture, et ils touchent aux portes de la mort.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Alors ils ont crié à l’Éternel dans leur détresse, [et] il les a délivrés de leurs angoisses.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Il a envoyé sa parole et les a guéris, et les a retirés de leurs fosses.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Qu’ils célèbrent l’Éternel pour sa bonté, et pour ses merveilles envers les fils des hommes,
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
Et qu’ils sacrifient des sacrifices d’actions de grâces, et qu’ils racontent ses œuvres avec des chants de joie!
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Ceux qui descendent sur la mer dans des navires, qui font [leur] travail sur les grandes eaux,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Ceux-là voient les œuvres de l’Éternel, et ses merveilles dans les [eaux] profondes.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Il a commandé, et a fait venir un vent de tempête, qui souleva ses flots:
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Ils montent aux cieux, ils descendent aux abîmes: leur âme se fond de détresse;
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Ils tournent et chancellent comme un homme ivre, et toute leur sagesse est venue à néant…
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Alors ils ont crié à l’Éternel dans leur détresse, et il les a fait sortir de leurs angoisses;
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Il arrête la tempête, [la changeant] en calme, et les flots se taisent,
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Et ils se réjouissent de ce que les [eaux] sont apaisées, et il les conduit au port qu’ils désiraient.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Qu’ils célèbrent l’Éternel pour sa bonté, et pour ses merveilles envers les fils des hommes;
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Et qu’ils l’exaltent dans la congrégation du peuple, et le louent dans l’assemblée des anciens!
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
Il change les fleuves en désert, et les sources d’eaux en sol aride,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
La terre fertile en terre salée, à cause de l’iniquité de ceux qui y habitent.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Il change le désert en un étang d’eau, et la terre aride en des sources d’eaux;
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
Et il y fait habiter les affamés; et ils y établissent des villes habitables,
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
Et sèment les champs, et plantent des vignes, qui leur rapportent du fruit.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Et il les bénit, et ils se multiplient beaucoup; et il ne laisse pas diminuer leur bétail; …
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Et ils diminuent, et sont accablés par l’oppression, le malheur, et le chagrin.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
Il verse le mépris sur les nobles, et les fait errer dans un désert où il n’y a pas de chemin;
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
Mais il relève le pauvre de l’affliction, et donne des familles comme des troupeaux.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Les hommes droits le verront et s’en réjouiront; et toute iniquité fermera sa bouche.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Qui est sage prendra garde à ces choses, et comprendra les bontés de l’Éternel.