< Psalms 107 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Alleluya. Knouleche ye to the Lord, for he is good; for his merci is in to the world.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Sei thei, that ben ayen bouyt of the Lord; whiche he ayen bouyte fro the hond of the enemye, fro cuntreis he gaderide hem togidere.
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Fro the risyng of the sunne, and fro the goyng doun; fro the north, and fro the see.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Thei erriden in wildirnesse, in a place with out watir; thei founden not weie of the citee of dwellyng place.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Thei weren hungri and thirsti; her soule failide in hem.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
And thei crieden to the Lord, whanne thei weren set in tribulacioun; and he delyuerede hem fro her nedynesses.
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
And he ledde forth hem in to the riyt weie; that thei schulden go in to the citee of dwelling.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
The mercies of the Lord knouleche to hym; and hise merueilis knouleche to the sones of men.
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
For he fillide a voide man; and he fillide with goodis an hungry man.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
God delyuerede men sittynge in derknessis, and in the schadowe of deth; and men prisoned in beggerye and in yrun.
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
For thei maden bitter the spechis of God; and wraththiden the councel of the hiyeste.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
And the herte of hem was maad meke in trauelis; and thei weren sijk, and noon was that helpide.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
And thei crieden to the Lord, whanne thei weren set in tribulacioun; and he delyuerede hem from her nedynessis.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
And he ledde hem out of derknessis, and schadowe of deth; and brak the boondis of hem.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
The mercies of the Lord knouleche to hym; and hise merueils knouleche to the sones of men.
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
For he al to-brak brasun yatis; and he brak yrun barris.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
He vptook hem fro the weie of her wickidnesse; for thei weren maad lowe for her vnriytfulnesses.
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
The soule of hem wlatide al mete; and thei neiyeden `til to the yatis of deth.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
And thei crieden to the Lord, whanne thei weren set in tribulacioun; and he delyuerede hem fro her nedynessis.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
He sente his word, and heelide hem; and delyuerede hem fro the perischingis of hem.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
The mercies of the Lord knouleche to hym; and hise merueils to the sones of men.
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
And offre thei the sacrifice of heriyng; and telle thei hise werkis in ful out ioiyng.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Thei that gon doun in to the see in schippis; and maken worching in many watris.
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Thei sien the werkis of the Lord; and hise merueilis in the depthe.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
He seide, and the spirit of tempest stood; and the wawis therof weren arerid.
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Thei stien til to heuenes, and goen doun `til to the depthis; the soule of hem failide in yuelis.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Thei weren troblid, and thei weren moued as a drunkun man; and al the wisdom of hem was deuourid.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
And thei crieden to the Lord, whanne thei weren set in tribulacioun; and he ledde hem out of her nedynessis.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
And he ordeynede the tempest therof in to a soft wynde; and the wawis therof weren stille.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
And thei weren glad, for tho weren stille; and he ladde hem forth in to the hauene of her wille.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
The mercies of the Lord knouleche to hym; and hise merueilis to the sones of men.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
And enhaunse thei him in the chirche of the puple; and preise thei him in the chaier of eldre men.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
He hath set floodis in to deseert; and the out goingis of watris in to thirst.
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
He hath set fruytful lond in to saltnesse; for the malice of men dwellyng ther ynne.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
He hath set deseert in to pondis of watris; and erthe with out watir in to outgoyngis of watris.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
And he settide there hungri men; and thei maden a citee of dwelling.
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
And thei sowiden feeldis, and plauntiden vynes; and maden fruyt of birthe.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
And he blesside hem, and thei weren multiplied greetli; and he made not lesse her werk beestis.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
And thei weren maad fewe; and thei weren trauelid of tribulacioun of yuelis and of sorewis.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
Strijf was sched out on princes; and he made hem for to erre without the weie, and not in the weie.
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
And he helpide the pore man fro pouert; and settide meynees as a scheep bringynge forth lambren.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Riytful men schulen se, and schulen be glad; and al wickidnesse schal stoppe his mouth.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Who is wijs, and schal kepe these thingis; and schal vndirstonde the mercies of the Lord?

< Psalms 107 >