< Psalms 107 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Give thanks to Yahweh, because he always does good [things for us] His faithful love [for us] lasts forever!
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Those whom Yahweh has saved should tell others that he has rescued them from their enemies.
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
He has gathered [those of you] who were [(exiled/taken forcefully)] to many lands; [he has gathered you together from] the east and the west, from the north and from the south.
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Some of those [who returned from those countries] wandered in the desert; they were lost and had no homes to live in.
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
They were hungry and thirsty, and they were very discouraged.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
When they were in trouble, they called out to Yahweh, and he rescued them from (being distressed/their difficulties).
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
He led them along a straight road [where they walked safely] to cities [in Canaan] where they could live.
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
They should praise/thank Yahweh for loving them faithfully and for the wonderful things that he does for people.
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
He gives thirsty people plenty [of water] to drink, and he gives hungry people plenty of good things [to eat].
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Some of them were in very dark [HEN] (places [in Babylonia/other countries]); they were prisoners, suffering because of chains [fastened to their hands and feet].
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
They were in prison because they had (rebelled against/not obeyed) the message of God; they were there because they had despised the advice given by God, who is greater than all other gods.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
[That is why] their bodies were worn out from hard labor; when they fell down, there was no one who would help them.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
In their troubles, they called out to Yahweh, and he rescued them from their being distressed.
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
He broke the chains that were on their hands and feet; and brought them out of those very dark [prisons].
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
He broke down the [prison] gates that were made of bronze, and cut through the [prison] bars that were made of iron. [So they also] should praise/thank Yahweh for faithfully loving [them], and for [all] the wonderful things that he does for people.
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Some of them foolishly rebelled [against God], so they suffered for their sins.
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
They did not want to eat any food, and they almost died.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
In their troubles, they [also] called out to Yahweh, and he rescued them from their being distressed.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
When he commanded that they be healed, they were healed; he saved them from dying.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
They [also] should praise/thank Yahweh for faithfully loving them, and for [all] the wonderful things that he does for people.
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
They should give offerings to him to show that they are thankful, and they should sing joyfully about the miracles that he has performed.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Some of them sailed in ships; they were selling things [in ports] throughout the world.
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
[As they were sailing], they also saw the miracles that Yahweh performed, the wonderful things that he did [when they were] on very deep seas.
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
He commanded the winds, and they became strong and (stirred up high waves/caused waves to rise high).
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
The ships [in which they were sailing] were tossed high in the air, and [then] they sank into the (troughs/low places) [between the high waves]; then the sailors were terrified.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
They stumbled about and staggered like drunken men, and they did not know what to do.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
In their troubles, they [also] called out to Yahweh, and he rescued them from their distresses.
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
He (calmed the storm/caused the wind to stop blowing), and he caused the waves to completely subside.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
They were [very] glad when it became calm; and Yahweh brought them safely into a harbor.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
They [also] should praise/thank Yahweh for faithfully loving [them], and for [all] the wonderful things that he does for people.
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
They should praise him among the [Israeli] people when they have gathered together, and they should praise him in front of the leaders [of the country].
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
[Sometimes] Yahweh causes rivers [to become dry], [with the result that the land] becomes a desert, and springs of water become dry land.
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
[Sometimes] he causes land that has produced lots of crops to become salty wastelands, [with the result that they do not produce crops]. He does that because the people who live there are [very] wicked.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
[But sometimes] he causes pools of water to appear in deserts, and he causes springs to flow in very dry ground.
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
He brings hungry [people] into that land, to live there and build cities [there].
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
They plant seeds in their fields, and they plant grapevines that produce big crops [of grapes].
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
He blesses the people, and the women give birth to many children, and they have large herds of cattle.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
When the number of people becomes smaller and they have been humiliated [by their enemies] by being oppressed and caused to suffer [DOU],
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
Yahweh shows contempt for the leaders who oppress them, and causes them to wander in deserts where there are no roads.
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
But he rescues poor [people] from (being in misery/suffering), and causes their families [to increase in number] like flocks of sheep.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Godly/Righteous [people will (see/hear about)] these things, and they will rejoice, and wicked people [will hear about these things, too], [but] they will have nothing to say in reply.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Those who are wise should think carefully about those things; they should consider [all the things] that Yahweh [has done to show that he] faithfully loves [them].

< Psalms 107 >