< Psalms 107 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Славете Господа, защото е благ, Защото неговата милост трае до века.
2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Така нека говорят изкупените от Господа, Които Той изкупи от ръката на противника,
3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, láti àríwá àti Òkun wá.
Като ги събра от страните, От изток и от запад, от север и от юг
4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí, wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí wọn ó máa gbé.
Едни се скитат по пустинята, по усамотен път, Без да намират населен град
5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n, ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Гладни и жадни, Душата им примираше в тях.
6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Тогава извикаха към Господа в бедствието си; И Той ги избави от утеснениеята им,
7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú tí wọn lè máa gbé.
И заведе ги през прав път, За да отидат в населен град
8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Да славословят Господа за Неговата благост, И за чудесните Му дела към човешките чада;
9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.
Защото насища жадна душа, И гладна душа изпълня с блага.
10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,
Други седяха в тъмнина и в мрачна сянка, Вързани със скръб и и с желязо,
11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,
Защото се разбунтуваха против Божиите слова. И презряха съвета на Всевишния.
12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀; wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.
Затова смири сърцето им с труд; Те паднаха и нямаше кой да им помогне.
13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn
Тогава извикаха към Господа в бедствието си; И Той ги избави от утесненията им;
14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú òkùnkùn àti òjìji ikú, ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.
Изведе ги из тъмнината и мрачната сянка. И разкъса оковите им.
15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.
Да славословят Господа за Неговата благост, И за чудесните Му дела към човешките чада;
16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.
Защото разби медните порти, И железните лостове сломи.
17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
А пък безумните са в скръб поради беззаконните си пътища И поради неправдите си.
18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.
Душата им се гнуси от всяко ястие, А те се приближават до портите на смъртта.
19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn, ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.
Тогава викат към Господа в бедствието си; И Той ги избавя от утесненията им.
20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.
Изпраща словото Си та ги изцелява, И ги отървава от ямите, в които лежат.
21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Да славословят Господа за Неговата благост, И за чудесните Му дела към човешките чада;
22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́ kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.
И нека принасят жертви на хвала, И радостно възвестяват делата Му.
23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.
Ония пък, които слизат на морето в кораби, И вършат работи в големи води,
24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa, àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.
Те виждат делата на Господа, И чудесата Му в дълбочините,
25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́ tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.
Защото, когато заповядва и дига бурния вятър, Който повдига морските вълни,
26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú: nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.
Те се издигат до небесата, и пак се спущат до дълбочините Душата им се топи от бедствие.
27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn: ọgbọ́n wọn sì dé òpin.
Люлеят се и политат като пияни, И целият им разсъдък ги напуща.
28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè sí Olúwa nínú ìdààmú wọn, ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.
Тогава викат към Господа в бедствието си; И Той ги извежда от утесненията им;
29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́ bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.
Превръща бурята в тишина, И вълните й утихват.
30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀, ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.
Тогава те се веселят защото са утихнали; Така Той ги завежда на желаното от тях пристанище.
31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
Да славословят Господа за неговата благост, И за чудесните Му дела към човешките чада;
32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.
Нека Го и възвисяват в събранието на людете, И нека Го хвалят в заседанието на старейшините.
33 Ó sọ odò di aginjù, àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
Той превръща реки в пустиня, И водни извори в суша,
34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.
Плодородна земя в солена пустота, Поради нечестието на жителите й.
35 O sọ aginjù di adágún omi àti ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,
Превръща пустиня във водни езера, И суха земя във водни извори;
36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà, wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.
И там заселва гладните, За да си основават градове за живеене,
37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà tí yóò máa so èso tí ó dára;
И сеят ниви и садят лозя, И си добиват плодове и рожба.
38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.
Той ги и благославя, тъй щото те много се умножават, И не дава да се намалява добитъкът им.
39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú, ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,
Но пак, те се намаляват и се смиряват От угнетение, бедствие и тъга.
40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.
Той излива презрение върху князете, И ги правят да се скитат в пустиня, гдето няма път;
41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.
А немотният поставя на високо от неволя, И му дава челяд като стадо.
42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
Праведните виждат това и се радват; А всяко беззаконие си затваря устата.
43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.
Който е мъдър нека внимава на това; И нека размишляват човеците за Господните милости.