< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Halleluja! Tacken HERREN, ty han är god, ty hans nåd varar evinnerligen.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Vem kan uttala HERRENS väldiga gärningar och förkunna allt hans lov?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Saliga äro de som akta på vad rätt är, de som alltid öva rättfärdighet.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Tänk på mig, HERRE, efter din nåd mot ditt folk, besök mig med din frälsning,
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
så att jag med lust får se dina utvaldas lycka, glädja mig med ditt folks glädje, berömma mig med din arvedel.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Vi hava syndat likasom våra fäder, vi hava gjort illa, vi hava varit ogudaktiga.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Våra fäder i Egypten aktade icke på dina under; de tänkte icke på dina många nådegärningar, utan voro gensträviga vid havet, invid Röda havet.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Men han frälste dem för sitt namns skull, för att göra sin makt kunnig.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Han näpste Röda havet, så att det blev torrt, och förde dem genom djupen såsom genom en öken.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Han frälste dem från deras motståndares hand och förlossade dem ifrån fiendens hand.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
Vattnet övertäckte deras ovänner; icke en enda av dem blev kvar.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
Då trodde de på hans ord, då sjöngo de hans lov.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Men snart glömde de hans gärningar, de förbidade icke hans råd.
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
De grepos av lystnad i öknen och frestade Gud i ödemarken.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
Då gav han dem vad de begärde, men sände tärande sjukdom över dem.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Och de upptändes av avund mot Mose i lägret, mot Aron, HERRENS helige.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
Men jorden öppnade sig och uppslukade Datan och övertäckte Abirams hop.
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
Och eld begynte brinna i deras hop, en låga brände upp de ogudaktiga.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
De gjorde en kalv vid Horeb och tillbådo ett gjutet beläte;
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
sin ära bytte de bort mot bilden av en oxe, som äter gräs.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
De glömde Gud, sin frälsare, som hade gjort så stora ting i Egypten,
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
så underbara verk i Hams land, så fruktansvärda gärningar vid Röda havet.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Då hotade han att förgöra dem; men Mose, den man som han hade utvalt, trädde fram såsom medlare inför honom till att avvända hans vrede, så att den icke skulle fördärva.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
De föraktade det ljuvliga landet och trodde icke på hans ord.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
De knorrade i sina tält och lyssnade icke till HERRENS röst.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Då lyfte han upp sin hand mot dem och svor att slå ned dem i öknen,
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
att slå ned deras barn ibland hedningarna och förströ dem i länderna.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Och de slöto sig till Baal-Peor och åto det som var offrat åt döda.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
De förtörnade Gud med sina gärningar, och en hemsökelse bröt in över dem.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Men Pinehas trädde fram och skipade rätt, och så upphörde hemsökelsen;
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
det vart honom räknat till rättfärdighet från släkte till släkte, för evig tid.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
De förtörnade honom ock vid Meribas vatten, och det gick Mose illa för deras skull.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
Ty de voro gensträviga mot hans Ande, och han talade obetänksamt med sina läppar.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
De förgjorde icke de folk om vilka HERREN hade givit dem befallning,
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
utan beblandade sig med hedningarna och lärde sig deras gärningar.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
De tjänade deras avgudar, och dessa blevo dem till en snara.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Och de offrade sina söner och döttrar till offer åt onda andar.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Ja, de utgöto oskyldigt blod, sina söners och döttrars blod och offrade dessa åt Kanaans avgudar; och landet vart ohelgat genom blodskulder.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
Så blevo de orena genom sina gärningar och betedde sig trolöst i sina verk.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
Då upptändes HERRENS vrede mot hans folk, och hans arvedel blev honom en styggelse.
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
Och han gav dem i hedningars hand, så att de som hatade dem fingo råda över dem.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Deras fiender trängde dem, och de blevo kuvade under deras hand.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Många gånger räddade han dem, men de voro gensträviga i sin egenvilja och förgingos så genom sin missgärning.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
Men han såg till dem i deras nöd, när han hörde deras rop.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
Och han tänkte, dem till fromma, på sitt förbund och ömkade sig efter sin stora nåd.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Och han lät dem finna barmhärtighet inför alla dem som hade fört dem i fångenskap.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Fräls oss, HERRE, vår Gud, och församla oss från hedningarna, så att vi få prisa ditt heliga namn och berömma oss av ditt lov. ----
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Lovad vare HERREN, Israels Gud, från evighet till evighet! Och allt folket säge: "Amen, Halleluja!" Femte boken

< Psalms 106 >