< Psalms 106 >
1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Louvado seja Yahweh! Agradeça a Yahweh, pois ele é bom, pois sua bondade amorosa perdura para sempre.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Quem pode proferir os poderosos atos de Yahweh, ou declarar todos os seus elogios?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Bem-aventurados os que guardam a justiça. Abençoado é aquele que faz o que é certo em todos os momentos.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Lembre-se de mim, Yahweh, com o favor que você mostra ao seu povo. Visite-me com sua salvação,
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
para que eu possa ver a prosperidade de sua escolha, que eu possa me regozijar com a alegria de sua nação, para que eu possa me gloriar com sua herança.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
We pecaram com nossos pais. Cometemos iniquidade. Fizemos maldades.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Nossos pais não entenderam suas maravilhas no Egito. Eles não se lembravam da multidão de suas carinhosas gentilezas, mas eram rebeldes no mar, mesmo no Mar Vermelho.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Nevertheless ele os salvou por causa de seu nome, que ele possa tornar conhecido seu poderoso poder.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
He também repreendeu o Mar Vermelho, e ele estava seco; por isso os conduziu através das profundezas, como através de um deserto.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Ele os salvou da mão daquele que os odiava, e os resgatou da mão do inimigo.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
As águas cobriam seus adversários. Não sobrou nenhum deles.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
Then eles acreditaram em suas palavras. Eles cantaram seus louvores.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Eles logo esqueceram suas obras. Eles não esperaram por seu conselho,
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
but cedeu ao desejo de ceder no deserto, e testou Deus no terreno baldio.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
Ele lhes fez seu pedido, mas mandou a magreza para dentro de sua alma.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Eles invejavam Moisés também no acampamento, e Aaron, o santo de Yahweh.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
A terra se abriu e engoliu o Dathan, e cobriu a empresa de Abiram.
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
A fogo foi acendido em sua empresa. A chama queimou os malvados.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Eles fizeram um bezerro em Horeb, e adoravam uma imagem derretida.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Thus eles trocaram sua glória para uma imagem de um touro que come grama.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Eles se esqueceram de Deus, seu Salvador, que tinham feito grandes coisas no Egito,
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
obras maravilhosas na terra de Ham, e coisas incríveis junto ao Mar Vermelho.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Portanto, ele disse que iria destruí-los, se Moisés, seu escolhido, não estivesse diante dele na brecha, para desviar sua ira, para que não os destruísse.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
Yes, eles desprezaram a terra agradável. Eles não acreditaram na sua palavra,
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
mas murmurado em suas tendas, e não ouviu a voz de Javé.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Therefore ele jurou a eles que ele os derrubaria no deserto,
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
que ele derrubaria a descendência deles entre as nações, e os espalhe pelas terras.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Eles se uniram também a Baal Peor, e comeu os sacrifícios dos mortos.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
Thus eles o provocaram à raiva com seus atos. A praga os invadiu.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Então Phinehas se levantou e executou o julgamento, Assim, a peste foi detida.
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
Isso foi creditado a ele por justiça, para todas as gerações vindouras.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Eles também o enfureceram com as águas do Meribah, de modo que Moisés ficou perturbado por causa deles;
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
porque eles se rebelaram contra seu espírito, ele falou precipitadamente com seus lábios.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Eles não destruíram os povos, como Yahweh lhes ordenou,
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
but se misturaram com as nações, e aprenderam seus trabalhos.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Eles serviram seus ídolos, o que se tornou uma armadilha para eles.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Yes, eles sacrificaram seus filhos e suas filhas a demônios.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Eles derramam sangue inocente, mesmo o sangue de seus filhos e de suas filhas, que eles sacrificaram aos ídolos de Canaã. A terra foi poluída com sangue.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
Thus eles foram contaminados com suas obras, e se prostituíram em seus atos.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
Portanto Yahweh ardeu de raiva contra seu povo. Ele abominava sua herança.
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
Ele os entregou na mão das nações. Aqueles que os odiavam governavam sobre eles.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Seus inimigos também os oprimiram. Eles foram subjugados sob suas mãos.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
He resgatou-os muitas vezes, mas eles foram rebeldes em seus conselhos, e foram trazidos para baixo em sua iniquidade.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
Nevertheless ele considerou a aflição deles, quando ele ouviu o choro deles.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
Ele lembrou por eles seu convênio, e se arrependeu de acordo com a multidão de suas carinhosas gentilezas.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Ele fez com que eles também ficassem com pena por todos aqueles que os carregaram em cativeiro.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Salve-nos, Yahweh, nosso Deus, nos reúne entre as nações, para dar graças ao seu santo nome, para triunfar em seus louvores!
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Bendito seja Yahweh, o Deus de Israel, da eternidade até a eternidade! Que todas as pessoas digam: “Amém”. Louvado seja Yah!