< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Halleluja. Wysławiajcie Pana; albowiem dobry, albowiem na wieki miłosierdzie jego.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Któż wysłowi niezmierną moc Pańską, a wypowie wszystkę chwałę jego?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Błogosławieni, którzy strzegą sądu, a czynią sprawiedliwość na każdy czas.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Pamiętaj na mię, Panie! dla miłości ku ludowi swemu; nawiedźże mię zbawieniem swojem,
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
Abym używał dobrego z wybranymi twoimi, a weselił się w radości narodu twego, i chlubił się wespół z dziedzictwem twojem.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Zgrzeszyliśmy z ojcami swymi; niesprawiedliwieśmy czynili, i nieprawość popełniali.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Ojcowie nasi w Egipcie nie zrozumieli cudów twoich, ani pamiętali na wielkość miłosierdzia twego; ale odpornymi byli przy morzu Czerwonem.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
A wszakże ich wyswobodził dla imienia swego, aby oznajmił moc swoję.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Bo zgromił morze Czerwone, i wyschło, a przewiódł ich przez przepaści, jako przez puszczę.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
A tak zachował ich od ręki tego, który ich miał w nienawiści, a wykupił ich z ręki nieprzyjacielskiej.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
W tem okryły wody tych, którzy ich ciążyli; nie został ani jeden z nich.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
A choć uwierzyli słowom jego, i wysławiali chwałę jego:
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Przecież prędko zapomnieli na sprawy jego, i nie czekali na rady jego.
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
Ale zdjęci będąc chciwością na puszczy, kusili Boga na pustyniach.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
I dał im, czego żądali, a wszakże przepuścił suchoty na nich.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Zatem gdy się wzruszyli zawiścią przeciw Mojżeszowi w obozie, i przeciw Aaronowi, świętemu Pańskiemu:
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
Otworzyła się ziemia, i pożarła Datana, i okryła rotę Abironową,
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
I zapalił się ogień na zebranie ich; płomień spalił niepobożnych.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Sprawili i cielca na Horebie, i kłaniali się bałwanowi litemu,
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
I odmienili chwałę swą w podobieństwo wołu, jedzącego trawę.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Zapomnieli na Boga, wybawiciela swego, który czynił wielkie rzeczy w Egipcie;
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
Rzeczy dziwne w ziemi Chamowej, rzeczy straszne przy morzu Czerwonem.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Przetoż rzekł, że ich chciał wytracić, gdyby się był Mojżesz, wybrany jego, nie stawił w onem rozerwaniu przed nim, a nie odwrócił popędliwości jego, aby ich nie tracił.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
Wzgardzili też ziemią pożądaną, nie wierząc słowu jego.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
I szemrząc w namiotach swoich, nie byli posłuszni głosowi Pańskiemu.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Przetoż podniósł rękę swoję przeciwko nim, aby ich pobił na puszczy;
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
A żeby rozrzucił nasienie ich między pogan, i rozproszył ich po ziemiach.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Sprzęgli się też byli z bałwanem Baalfegorem, a jedli ofiary umarłych.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
A tak draźnili Boga sprawami swemi, że się na nich oborzyła plaga;
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Aż się zastawił Finees, a pomstę uczynił, i rozerwana jest ona plaga;
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
Co mu poczytano ku sprawiedliwości od narodu do narodu, aż na wieki.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Znowu go byli wzruszyli do gniewu u wód Meryba, tak, iż się źle działo i z Mojżeszem dla nich.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
Albowiem rozdraźnili ducha jego, że wyrzekł co niesłuszne usty swemi.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Nadto nie wytracili onych narodów, o których im był Pan powiedział.
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
Ale pomięszawszy się z onemi narodami, nauczyli się spraw ich:
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
I służyli bałwanom ich, które im były sidłem.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Albowiem dyjabłom ofiarowali synów swoich, i córki swoje,
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
I wylewali krew niewinną, krew synów swoich, i córek swoich, których ofiarowali bałwanom rytym Chananejskim, tak, że splugawiona była ziemia onem krwi rozlaniem.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
I zmazali się sprawami swemi, a cudzołożyli wynalazkami swemi.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
Przetoż zapaliwszy się Pan w popędliwości przeciw ludowi swemu, obrzydził sobie dziedzictwo swoje,
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
I podał ich w ręce poganom; a panowali nad nimi, którzy ich mieli w nienawiści;
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
I uciskali ich nieprzyjaciele ich, tak, że poniżeni byli pod ręką ich.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Częstokroć ich wybawiał; wszakże go oni wzruszali do gniewu radami swemi, zaczem poniżeni byli dla nieprawości swoich.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
A wszakże wejrzał na ucisk ich, i usłyszał wołanie ich.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
Bo sobie wspomniał na przymierze swoje z nimi, a żałował tego według wielkiej litości swojej.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Tak, że im zjednał miłosierdzie przed oczyma wszystkich, którzy ich byli pojmali.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Wybawże nas, Panie, Boże nasz! a zgromadź nas z tych pogan, abyśmy wysławiali imię świętobliwości twojej, a chlubili się w chwale twojej.
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, od wieków aż na wieki; na co niech rzecze wszystek lud: Amen, Halleluja.

< Psalms 106 >