< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Alleluja! Pateiciet Tam Kungam, jo Viņš ir labs, un Viņa žēlastība paliek mūžīgi.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Kas var izteikt Tā Kunga varenos darbus un izstāstīt visu Viņa teicamo slavu?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Svētīgi tie, kas tiesu tur un dara taisnību vienmēr.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Piemini mani, ak Kungs, pēc Sava labā prāta uz Saviem ļaudīm, piemeklē mani ar Savu pestīšanu;
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
Ka redzam labumu pie Taviem izredzētiem un priecājamies par Tavu ļaužu prieku un lielāmies ar Tavu īpašumu.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Mēs esam grēkojuši līdz ar saviem tēviem, esam noziegušies un bijuši bezdievīgi.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Mūsu tēvi Ēģiptē nelika vērā Tavus brīnumus, tie nepieminēja Tavu lielo žēlastību, bet bija pārgalvīgi jūrmalā pie niedru jūras.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Viņš tiem palīdzēja Sava vārda dēļ, ka tiem parādītu Savu varu.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Un Viņš rāja niedru jūru, ka tā sasīka, un Viņš vadīja caur dziļumiem kā pa tuksnesi.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Un Viņš tos atpestīja no ienaidnieku rokas un tos atsvabināja no nīdētāju rokas.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
Ūdeņi apsedza viņu pretiniekus, ka neviens no tiem neatlika.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
Tad tie ticēja Viņa vārdiem, tie dziedāja Viņa slavu.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Bet steigšus tie aizmirsa Viņa darbus, tie nenogaidīja Viņa nodomu;
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
Bet kārot iekārojās tuksnesī un kārdināja Dievu tai posta vietā.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
Tad Viņš tiem deva pēc viņu kārības, bet darīja viņu dvēseles nīkstam.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Un tie apskauda Mozu lēģerī un Āronu, Tā Kunga svēto.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
Zeme atvērās un aprija Datanu un apklāja Abirama biedrus.
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
Un uguns iedegās viņu pulkā, liesma sadedzināja tos bezdievīgos.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Tie taisīja teļu Horebā un klanījās tās bildes priekšā,
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Un pārvērsa savu godu par vērša ģīmi, kas ēd zāli.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Viņi aizmirsa Dievu, savu Pestītāju, kas lielas lietas bija darījis Ēģiptes zemē,
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
Brīnumus Hama zemē, briesmīgus darbus pie niedru jūras.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Tā ka Viņš nodomāja tos izdeldēt, ja Mozus, Viņa izredzētais, nebūtu stājies tai plaisumā Viņa priekšā, novērst Viņa bardzību, lai nesamaitātu.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
Tie necienīja to jauko zemi, tie neticēja Viņa Vārdam,
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
Bet kurnēja savās teltīs un nepaklausīja Tā Kunga balsij.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Tāpēc Viņš pacēla pret tiem Savu roku, tos nosist tuksnesī
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
Un nogāzt viņu dzimumu starp pagāniem un tos izkaisīt pa tām zemēm.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Tie pieķērās arī BaālPeoram un ēda mirušu upurus,
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
Un apkaitināja To Kungu ar saviem darbiem, ka mocība starp viņiem ielauzās.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Tad Pinehas cēlās un sodīja, un tā mocība mitējās.
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
Un tas viņam tapa pielīdzināts par taisnību uz bērnu bērniem mūžīgi.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Un tie Viņu apkaitināja pie bāršanās ūdens, ka Mozum viņu dēļ ļaunums uzgāja.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
Jo tie padarīja viņa sirdi rūgtu, ka viņš neapdomīgi runāja ar savām lūpām.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Tie arī neizdeldēja tās tautas, kā Tas Kungs tiem bija pavēlējis;
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
Bet tie sajaucās ar pagāniem un mācījās viņu darbus;
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Un kalpoja viņu elkiem, un tie viņiem palika par valgu.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Pat savus dēlus un savas meitas tie upurēja nešķīstiem gariem,
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Un izlēja nenoziedzīgas asinis, savu dēlu un savu meitu asinis, ko tie upurēja Kanaāna elkiem, tā ka zeme tapa apgānīta caur asins vainām.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
Un tie sagānījās ar saviem darbiem un maukoja ar savām darīšanām.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
Par to Tas Kungs ļoti iedusmojās pret Saviem ļaudīm un turēja par negantību Savu īpašumu;
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
Un Viņš tos nodeva pagānu rokā, un viņu nīdētāji par tiem valdīja.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Un viņu ienaidnieki tos apbēdināja un tos pazemoja apakš savas rokas.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Viņš tos izglāba daudzkārt, taču tie Viņu apkaitināja ar savu padomu un iznīka savu noziegumu dēļ.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
Bet Viņš uzlūkoja viņu bēdas un dzirdēja viņu kliegšanu,
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
Un pieminēja viņu labad Savu derību, un Viņam bija žēl pēc Savas lielās žēlastības,
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Un lika tiem atrast sirds žēlastību pie visiem, kas tos turēja cietumā.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Atpestī mūs, Kungs, mūsu Dievs, un sapulcini mūs no tiem pagāniem, ka mēs pateicamies Tavam svētam vārdam un lielāmies ar Tavu slavu.
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Slavēts lai ir Tas Kungs, Israēla Dievs, mūžīgi mūžam, un visi ļaudis lai saka: Āmen! Alleluja.

< Psalms 106 >