< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Hallelúja! Adjatok hálát az Örökkévalónak, mert jóságos, mert örökké tart a kegyelme.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Ki mondhatja el az Örökkévaló hatalmas tetteit, hirdetheti minden dicséretét?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Boldogok, akik megőrzik a jogot, aki igazságot mível minden időben.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Emlékezzél reám, Örökkévaló, a néped iránt való kedvességgel, gondolj reám a te segítségeddel,
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
hogy láthassam választottaid jólétét, hogy örüljek nemzeted örömén, hogy dicsekedjem birtokoddal együtt.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Vétkeztünk, őseinkkel együtt, bűnt követtünk el, gonoszul cselekedtünk.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Őseink Egyiptomban nem fogták föl csodatetteidet, nem emlékeztek kegyeid bőségére s engedetlenkedtek a tenger mellett, a nádastengernél.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Megsegítette őket neve kedvéért, hogy tudassa hatalmát.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Megdorgálta a nádastengert és kiszáradt s vezette őket mélységekben, akár a pusztában.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Megsegítette őket gyülölőnek kezéből, megváltotta őket ellenségnek kezéből;
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
vizek borították be szorongatóikat, egy sem maradt meg közülök.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
És hittek szavaiban, énekelték dicséretét.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Hamar felejtették el tetteit, nem várták be határozatát:
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
vágygyal vágyakoztak a pusztában, s megkísértették Istent a sivatagban;
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
meg is adta nekik kérésöket, de soványságot bocsátott lelkökre.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Felbuzdúltak Mózes ellen a táborban, Áron, az Örökkévaló szentje ellen.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
Megnyílt a föld s elnyelte Dátánt, s befödte Abírám községét;
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
tűz égett községük között, láng lobbasztotta el a gonoszokat.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
készítettek borjút a Chórébnél, s leborultak öntött kép előtt.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Felcserélték dicsőségöket, képmásával ökörnek, füvet evőnek.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Elfelejtették Istent, segítőjüket, ki nagyokat mívelt Egyiptomban,
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
csodás tetteket Chám földjén, félelmeteseket a nádastenger mellett.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Kimondta, hogy megsemmisíti őket, hacsak Mózes az ő választottja nem áll a résben előtte, hogy elfordítsa hevét, nehogy rontson.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
Megvetették a gyönyörűséges országot, nem hittek igéjének;
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
zúgolódtak sátraikban, nem hallgattak az Örökkévaló szavára.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Akkor kezet emelt felőlük, hogy elejti őket a pusztában,
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
s hogy magzatukat a nemzetek közé ejti, s hogy szétszórja őket az országokban.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Csatlakoztak Báal-Peórhoz és ették halottaknak áldozatait;
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
bosszantották cselekedeteikkel és csapás tört ki köztük.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Akkor odaállt Pínechász s ítéletet tett és elállt a csapás;
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
betudatott az neki igazságul nemzedékre meg nemzedékre örökké.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Megharagították a pörlekedés vizénél, s rosszul járt Mózes ő miattuk,
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
mert engedetlenkedtek szelleme iránt, s elszólta magát ajkaival.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Nem semmisítették meg a népeket, melyeket mondott nekik az Örökkévaló;
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
hanem összevegyültek a nemzetekkel s eltanulták tetteiket.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Szolgálták bálványaikat, úgy hogy tőrül lettek nekik;
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
áldozták fiaikat és leányaikat a gonosz szellemeknek.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Ártatlan vért ontottak, fiaik és leányaik vérét, akiket áldoztak Kanaán bálványainak, úgy hogy fertőzötté lett az ország a vérbűntől.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
Tisztátalanokká lettek tetteik által s paráználkodtak cselekedeteikkel.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
És föllobbant az Örökkévaló haragja népe ellen, s megútálta birtokát;
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
adta őket nemzetek kezébe, s uralkodtak rajtuk gyülölőik,
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
szorították őket ellenségeik s megalázkodtak kezök alatt.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Sok ízben mentette meg őket, de ők engedetlenkedtek öntanácsuk szerint s összeroskadtak bűnükben.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
De látta szorultságukat, midőn meghallotta fohászukat;
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
s megemlékezett számukra szövetségéről és sajnálkozott kegyeinek bősége szerint,
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
s adta őket irgalomra mind a foglyulejtőik előtt.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Segíts meg minket, Örökkévaló, Istenünk, s gyűjts össze a nemzetek közül, hogy hálát adjunk szent nevednek, hogy magasztalódjunk dicséreteddel!
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Áldva legyen az Örökkévaló, Izraél Istene, öröktől fogva örökké. S mondja az egész nép: Ámen! Hallelúja!

< Psalms 106 >