< Psalms 106 >
1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
E HALELU aku ia Iehova. E mililani aku ia Iehova, no ka mea ua maikai ia; Ua mau loa hoi kona lokomaikai.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Owai la ka mea e hai mai i na mea nui a Iehova? A e hoike mai hoi i kona hanohano a pau?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Pomaikai ka poe malama i ka hoopono, A hana i ka pololei i na manawa a pau.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
E hoomanao mai oe ia'u, e Iehova, Me au e aloha'i i kou poe kanaka; E haawi mai no hoi ia'u i kou hoola ana.
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
I ike aku au i ka maikai o kou poe i waeia, I lealea hoi au ma ka lealea ana o kou lahuikanaka, I kaena hoi au ma kou poe hooilina.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Ua hewa pu no makou me ko makou poe kupuna, Ua lawehala hoi, a ua hana kolohe.
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
O ko makou poe kupuna ma Aigupita, Aole lakou i hoomaopopo i kau mau hana mana; Aole hoi lakou i hoomanao i ka nui o kou lokomaikai; A hoonaukiuki aku la ma ke kai, ma ke Kaiula hoi.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Aka, no kona inoa, hoola mai oia ia lakou, I hoike mai ai oia i kona mana.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Papa mai la oia i ke Kaiula, a maloo iho la ia; Alakai ae la oia ia lakou ma ka hohonu me he nahelehele la.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Hoola mai la oia ia lakou mai ka lima mai o ka poe inaina, A hoola panai hoi ia lakou mai ka lima mai o ka enemi.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
Popoi mai la na wai i ko lakou poe enemi; Aole i hookoeia kekahi o lakou.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
Alaila, hooiaio lakou i kana mau olelo, A oli iho la i mau halelu nona.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Poina koke ia lakou kana mau hana, Aole lakou i kakali i kana ao ana.
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
Kuko nui no lakou ma ka waonahele, A hoao lakou i ke Akua, ma ka waoakua.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
Haawi mai la oia ia lakou i ka mea a lakou i noi aku ai; A haawi mai nae i ka hookii iloko o ko lakou uhane.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Huahua lakou ia Mose ma kahi hoomoana'i, A me Aarona hoi ka haipule a Iehova.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
Wahi ae la ka honua, a moni iho la ia Datana, A poi mai la hoi maluna o ke anaina o Abirama,
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
Hoaaia ke ahi ma ko lakou anaina, A pau iho la ka poe hewa i ka lapalapa ahi.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Hana no lakou i keiki bipi ma Horeba, A kulou hoomana lakou ia kii hooheheeia.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Hoololi lakou i ko lakou nani I ke ano o ka bipi e ai ana i ka mauu.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Poina ia lakou ke Akua, ko lakou Hoola, Ka mea i hana i na mea nui ma Aigupita;
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
Na mea kupanaha hoi ma ka aina o Hama, Na mea weliweli hoi ma ke Kaiula.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Alaila, olelo no oia e luku ia lakou, Ina i ku ole o Mose, kona mea i waeia ma ka hakahaka imua ona. E pale aku i kona huhu i ole ia e luku mai.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
A hoowahawaha no hoi lakou i ka aina aloha, Aole hoi i hooiaio i kana olelo.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
Ohumu iho lakou ma ko lakou mau halelewa. Aole hoi i hoolohe i ka leo o Iehova.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Alaila, hoana ae la oia i kona lima, E hoohina ia lakou ma ka waonahele;
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
E hoohina hoi i ka lakou poe mamo mawaena o ko na aina e, A e hooauhee ia lakou maluna o ka honua.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Hoopili ae la lakou ia Baalapeora, A ai no hoi lakou i na mohai o ka poe i make.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
Hoonaukiuki aku lakou ma ka lakou hana ana; A puka mai la ka mai make iwaena o lakou.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Alaila ku ae la o Pinehasa iluna, a hoopai iho la, A hookiia ua mai make la.
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
Manaoia'e la ia, he pono nona, I kela hanauna, i keia hanauna, a mau loa aku.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Hoonaukiuki aku lakou ia ia ma na wai o Meriba, A hewa o Mose, no lakou la.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
No ka mea, hookuee lakou i ka manao ana, A olelo pono ole mai la oia ma kona mau lehelehe.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Aole lakou i luku ae i na lahuikanaka, A Iehova i kauoha mai ai ia lakou.
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
Ua huiia no lakou me ko na aina e, A ao mai la lakou i ka lakou mau hana.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Malama aku no hoi i ko lakou poe akua kii, A lilo ia i pahele na lakou.
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Alaila, mohai aku la lakou i ka lakou poe keikikane, A me ka lakou poe kaikamahine no na daimonio.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Hookahe ae la lakou i ke koko hala ole, I ke koko hoi o ka lakou poe keikikane, a me ka lakou poe kaikamahine, Na mea a lakou i mohai aku ai i na'kua kii o Kanaana; A hoohaumiaia ka aina i ke koko.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
A haumia no hoi lakou i ka lakou mau hana, A moe kolohe lakou me na mea a lakou i hana'i.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
Nolaila, hoaaia ka inaina o Iehova i kona poe kanaka, A hoopailua mai la oia i kona hooilina iho.
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
A haawi ae la ia ia lakou i ka lima o ko na aina e; A noho alii maluna o lakou ka poe inaina mai ia lakou.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Hookaumaha mai no hoi ko lakou poe enemi ia lakou, A hoohaahaaia mai no hoi malalo iho o ko lakou lima.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Hoopakele pinepine mai la oia ia lakou; Aka, hoonaukiuki aku lakou ia ia, ma ko lakou manao, A hokii iho la lakou no ko lakou hewa.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
Alaila, ike mai la oia i ko lakou pilikia, Ia ia i lohe ai i ko lakou olo pihe ana.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
A hoomanao mai la oia i kona berita me lakou, A minamina iho la oia, e like me ka nui o kona lokomaikai ana.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Alaila, haawi mai la oia ia lakou I ke alohaia imua o ka poe a pau i lawe pio ia lakou.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
E hoola mai oe ia makou, e Iehova, e ko makou Akua, E hoiliili mai ia makou, maiwaena mai o ko na aina e, I mililani aku makou i ka inoa hoano, A e hiilani aku hoi ma kou halelu.
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
E hoomaikaiia o Iehova, ke Akua o ka Iseraela, Mai kahiko loa mai, a mau loa aku no: E i mai no hoi na kanaka a pau, Amene. E halelu aku ia Iehova.