< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Et elle se referma sur la troupe d'Abiram.
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
Qui pourrait raconter les victoires de l'Éternel, Et publier toutes ses louanges?
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
Heureux ceux qui observent la justice, Qui font en tout temps ce qui est droit!
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Éternel, souviens-toi de moi, Toi qui es plein de bienveillance pour ton peuple. Viens, accorde-moi ton salut,
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
Afin que j'aie part au bonheur de tes élus, Que je me réjouisse de la joie de ton peuple. Et que je me glorifie avec ceux qui t'appartiennent!
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
Nous et nos pères, nous avons péché. Nous avons mal agi; nous sommes coupables!
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
Nos pères, en Egypte, ne furent pas attentifs à tes miracles; Ils ne se souvinrent pas de la multitude de tes bontés; Mais ils se révoltèrent près de la mer, Sur les bords de la mer Rouge.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
Dieu les sauva, pour l'amour de son nom, Afin de manifester sa puissance.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
Il menaça la mer Rouge, et elle fut mise à sec; Il les conduisit à travers les abîmes comme à travers le désert.
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
Il les délivra des mains de l'adversaire, Et les sauva des mains de l'ennemi.
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
Les flots recouvrirent leurs oppresseurs: Aucun de ces derniers ne put échapper.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
Alors ils crurent aux promesses de Dieu, Et ils chantèrent ses louanges.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
Bientôt, ils oublièrent ses oeuvres; Ils n'eurent pas confiance en ses desseins.
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
Ils se laissèrent gagner par la convoitise dans le désert. Et ils tentèrent Dieu dans la solitude.
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
Alors il accueillit favorablement leur demande, Mais il envoya parmi eux la mortalité.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
Pendant qu'ils campaient, ils furent jaloux de Moïse Et d'Aaron, le saint de l'Éternel.
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
La terre s'ouvrit; elle engloutit Dathan,
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
Le feu dévora leur troupe; La flamme consuma les méchants.
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Ils firent un veau d'or au pied de l'Horeb, Et ils se prosternèrent devant une image de fonte.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Ils échangèrent le Dieu qui était leur gloire, Contre l'image d'un boeuf qui broute l'herbe.
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
Ils oublièrent Dieu, leur libérateur. Qui avait accompli des prodiges en Egypte,
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
Des merveilles dans le pays de Cham, Et des oeuvres redoutables sur la mer Rouge.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Dieu parlait même de les anéantir; Mais Moïse, son élu, se tint sur la brèche en face de lui, Pour détourner sa colère et pour empêcher leur destruction.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
Ils méprisèrent une terre pleine de délices, Ne voulant pas croire à la promesse divine.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
Ils murmurèrent dans leurs tentes; Ils n'écoutèrent pas la voix de l'Éternel.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
Alors il leur fit le serment De les laisser périr dans le désert,
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
De laisser périr leur postérité parmi les nations. De les disperser dans tous les pays.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Ils s'attachèrent à Baal-Péor, Et mangèrent les sacrifices offerts à des dieux sans vie.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
Ils irritèrent Dieu par leurs crimes, Et la mortalité fondit sur eux.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
Mais Phinées se leva; il intervint, Et le fléau fut arrêté.
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
Son zèle lui fut imputé comme un acte de justice. Dans tous les âges, à perpétuité.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
Ils excitèrent aussi le courroux de l'Éternel Près des eaux de Mériba, Et Moïse fut affligé à cause d'eux;
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
Car ils aigrirent son esprit. De sorte qu'il prononça des paroles imprudentes.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Ils ne détruisirent pas les peuples Que l'Éternel leur avait ordonné d'anéantir.
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
Mais ils se mêlèrent aux autres nations. Et ils apprirent à faire comme elles.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Ils servirent leurs idoles. Qui furent pour eux un piège,
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
Et ils sacrifièrent aux démons leurs fils, Ainsi que leurs filles.
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
Ils répandirent le sang innocent, Le sang de leurs fils et de leurs filles, Qu'ils sacrifièrent aux idoles de Canaan; Et le pays fut profané par ces meurtres.
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
Ils se souillèrent par leurs actes impies, Et se déshonorèrent par leur conduite infâme.
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
La colère de l'Éternel s'enflamma contre son peuple; Il prit en aversion son héritage.
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
Il livra les Israélites entre les mains des nations; Ceux qui les haïssaient dominèrent sur eux.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Leurs ennemis les opprimèrent Et les firent plier sous leur pouvoir.
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Maintes fois, il les délivra; Mais eux se révoltaient, N'obéissant qu'à leurs mauvaises pensées, Et ils consommaient leur perte par leurs propres fautes.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
Toutefois, il les regarda dans leur détresse, Quand il entendit leur cri.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
Il se souvint en leur faveur de son alliance. Et il les prit en pitié, dans sa grande miséricorde.
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
Il leur fit trouver grâce Auprès de tous ceux qui les retenaient captifs.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Sauve-nous, ô Éternel, notre Dieu, Et rassemble-nous du sein des nations. Afin que nous célébrions ton saint nom. Et que nous mettions notre gloire à te louer!
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Béni soit l'Éternel, le Dieu d'Israël, De siècle en siècle, Et que tout le peuple dise: Amen! Louez l'Éternel!

< Psalms 106 >