< Psalms 106 >

1 Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
Praise Yahweh! Praise Yahweh, because he does good things [for us]; he faithfully loves [us] forever/continually!
2 Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
[Because Yahweh has done many great things], no one can [RHQ] tell all the great things that Yahweh has done, and no one can praise him enough/sufficiently.
3 Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
(Happy are/He is pleased with) those who act fairly/justly, with those who always do what is right.
4 Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
Yahweh, be kind to me when you help your people; help me when you rescue/save them.
5 kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
Allow me to see it when your people become prosperous again and when [all the people of] your nation, [Israel], are happy; allow me to be happy with them! I want to praise you along with [all] those [others] who belong to you.
6 Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
We and our ancestors have sinned; we have done things that were very wicked [DOU].
7 Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
When our ancestors were in Egypt, they did not pay attention to the wonderful things that Yahweh did; they forgot about the many times that he showed that he faithfully loved them. Instead, when they were at the Red Sea, they rebelled against God, who is greater than any other god.
8 Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
But he rescued them for the sake of his own [reputation] in order that he could show that he is very powerful.
9 O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
He rebuked the Red Sea and it became dry, and [then] while he led our ancestors across it, they walked through it as though it were as dry as a desert [SIM].
10 O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
In that way he rescued them from the power [MTY] of their enemies who hated them [DOU].
11 Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
[Then] their enemies were drowned in the water [of the Red Sea]; not one of them was left.
12 Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
When that happened, our ancestors believed [that Yahweh had truly done for them] what he had promised to do, and they sang to praise him.
13 Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
But they soon forgot what he had done for them; they [did things] without waiting to find out what Yahweh wanted them to do.
14 Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
They intensely wanted [food like they formerly ate in Egypt]. They [did evil things to] find out [if they could do those things without God punishing them].
15 Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
[So] he gave them what they requested, but he [also] caused a terrible disease to afflict them.
16 Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
[Later] when [some of] the men became jealous of Moses and [his older brother] Aaron, who was dedicated [to serve Yahweh by being a priest],
17 Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
the ground opened up and swallowed Dathan and [also] buried Abiram and his family.
18 Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
And [God sent] a fire down [from heaven] which burned up [all] the wicked [people who (supported them/agreed with) them].
19 Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
Then the [Israeli leaders] made a gold statue at Sinai [Mountain] and worshiped it.
20 Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
Instead of worshiping [our] glorious God, they [started to] worship a statue of a bull that eats grass!
21 Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
They forgot about God, who had rescued them by the great miracles that he performed in Egypt.
22 iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
They forgot about the wonderful things that he did for them in Egypt and the amazing/awesome things that he did for them at the Red Sea.
23 Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
Because of that, God said that he would get rid of the Israelis, but Moses, whom God had chosen [to serve him], pleaded with God [not to get rid of them]. And as a result God did not destroy them.
24 Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
[Later], our ancestors (refused/were afraid) to enter beautiful [Canaan] land because they did not believe [that God would enable them to take the land from the people who were living there, as] he had promised.
25 Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
They stayed in their tents and grumbled and would not pay attention to what Yahweh said that they should do.
26 Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
So he solemnly [MTY] told them that he would cause them to die [there] in the desert,
27 láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
and that he would scatter their descendants among the [people of other] nations/people-groups [who did not believe in him], and that he would allow them to die in those lands.
28 Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
Later the Israeli people [started to] worship [the idol of] Baal [who they thought lived] at Peor [Mountain], and they ate [meat that had been] sacrificed to [Baal and those other] lifeless gods.
29 wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
Yahweh became [very] angry because of what they had done, [so again] he sent a terrible disease to attack/strike them.
30 Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
But Phinehas stood up and punished/killed [the ones who had sinned greatly], and as a result the (plague/serious disease) ended.
31 A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
People have remembered that righteous thing that Phinehas did, and in future years people will remember it.
32 Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
[Then] at Meribah Springs our ancestors caused Yahweh to become angry, and as a result Moses had trouble.
33 Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
They caused Moses to become very angry [IDM], and he said things that were foolish.
34 Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
Our ancestors did not destroy the people [who did not believe in Yahweh] like he told them to do.
35 Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
Instead, they mingled with people from those people-groups, and they started to do the evil things that those people did.
36 Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
Our ancestors worshiped the idols of those people, which resulted in their being destroyed/exiled/taken to another country [MET].
37 Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
[Some of] the Israelis sacrificed their sons and daughters to the demons [that those idols represented].
38 Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
They killed [MTY] their own children, who (were innocent/had not done things that were wrong), and offered them as sacrifices to the idols in Canaan. [As a result], Canaan land was polluted by those murders [MTY].
39 Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
So by their deeds they caused themselves to become unacceptable to God; [because they did not faithfully worship only God], [they became like] women who sleep with other men [instead of sleeping only with their husbands] [MET].
40 Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
So Yahweh became very angry with his people; he was completely disgusted with them.
41 Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
[As a result] he allowed people-groups [who did not believe in him] to conquer them, so those who hated our ancestors started to rule over them.
42 Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
Their enemies (oppressed them/treated them cruelly) and completely controlled them [MET].
43 Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Many times Yahweh rescued them, but they continued to rebel against him, and they were finally destroyed because of the sins that they committed.
44 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
However, Yahweh [always] heard them when they cried out to him; he listened to them when they were distressed.
45 ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
For their sake, he thought about the agreement/promise that he had made [to bless] them, and because he never stopped loving them very much, he changed his mind [about punishing them more].
46 Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
He caused all those who had taken the Israelis [to Babylonia] to (feel sorry for/pity) them.
47 Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
Yahweh our God, rescue/save us and bring us back [to Israel] from among those people-groups in order that we may thank you [MTY] and joyfully praise you.
48 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!
Praise Yahweh, the God whom [we] Israelis [worship], praise him now and forever! And I want everyone to say, “Amen/May it be so!” Praise Yahweh!

< Psalms 106 >