< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
RAB'be şükredin, O'nu adıyla çağırın, Halklara duyurun yaptıklarını!
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
O'nu ezgilerle, ilahilerle övün, Bütün harikalarını anlatın!
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Kutsal adıyla övünün, Sevinsin RAB'be yönelenler!
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
RAB'be ve O'nun gücüne bakın, Durmadan O'nun yüzünü arayın!
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Ey sizler, kulu İbrahim'in soyu, Seçtiği Yakupoğulları, O'nun yaptığı harikaları, Olağanüstü işlerini Ve ağzından çıkan yargıları anımsayın!
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Tanrımız RAB O'dur, Yargıları bütün yeryüzünü kapsar.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
O antlaşmasını, Bin kuşak için verdiği sözü, İbrahim'le yaptığı antlaşmayı, İshak için içtiği andı sonsuza dek anımsar.
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
“Hakkınıza düşen mülk olarak Kenan ülkesini size vereceğim” diyerek, Bunu Yakup için bir kural, İsrail'le sonsuza dek geçerli bir antlaşma yaptı.
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
O zaman bir avuç insandılar, Sayıca az ve ülkeye yabancıydılar.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Bir ulustan öbürüne, Bir ülkeden ötekine dolaşıp durdular.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
RAB kimsenin onları ezmesine izin vermedi, Onlar için kralları bile payladı:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
“Meshettiklerime dokunmayın, Peygamberlerime kötülük etmeyin!” dedi.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Ülkeye kıtlık gönderdi, Bütün yiyeceklerini yok etti.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Önlerinden bir adam göndermişti, Köle olarak satılan Yusuf'tu bu.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Zincir vurup incittiler ayaklarını, Demir halka geçirdiler boynuna,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Söyledikleri gerçekleşinceye dek, RAB'bin sözü onu sınadı.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Kral adam gönderip Yusuf'u salıverdi, Halklara egemen olan onu özgür kıldı.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Onu kendi sarayının efendisi, Bütün varlığının sorumlusu yaptı;
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Önderlerini istediği gibi eğitsin, İleri gelenlerine akıl versin diye.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
O zaman İsrail Mısır'a gitti, Yakup Ham ülkesine yerleşti.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
RAB halkını alabildiğine çoğalttı, Düşmanlarından sayıca artırdı onları.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Sonunda tutumunu değiştirdi düşmanlarının: Halkından tiksindiler, Kullarına kurnazca davrandılar.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Kulu Musa'yı, Seçtiği Harun'u gönderdi aralarına.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Onlar gösterdiler RAB'bin belirtilerini, Ham ülkesinde şaşılası işlerini.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Karanlık gönderip ülkeyi karanlığa bürüdü RAB, Çünkü Mısırlılar O'nun sözlerine karşı gelmişti.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Kana çevirdi sularını, Öldürdü balıklarını.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Ülkede kurbağalar kaynaştı Krallarının odalarına kadar.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
RAB buyurunca sinek sürüleri, Sivrisinekler üşüştü ülkenin her yanına.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Dolu yağdırdı yağmur yerine, Şimşekler çaktırdı ülkelerinde.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Bağlarını, incir ağaçlarını vurdu, Parçaladı ülkenin ağaçlarını.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
O buyurunca çekirgeler, Sayısız yavrular kaynadı.
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Ülkenin bütün bitkilerini yediler, Toprağın ürününü yiyip bitirdiler.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
RAB ülkede ilk doğanların hepsini, İlk çocuklarını öldürdü.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
İsrailliler'i ülkeden altın ve gümüşle çıkardı, Oymaklarından tek kişi bile tökezlemedi.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Onlar gidince Mısır sevindi, Çünkü İsrail korkusu çökmüştü Mısır'ın üzerine.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
RAB bulutu bir örtü gibi yaydı üzerlerine, Gece ateş verdi yollarını aydınlatsın diye.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
İstediler, bıldırcın gönderdi, Göksel ekmekle doyurdu karınlarını.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Kayayı yardı, sular fışkırdı, Çorak topraklarda bir ırmak gibi aktı.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Çünkü kutsal sözünü, Kulu İbrahim'e verdiği sözü anımsadı.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Halkını sevinç içinde, Seçtiklerini sevinç çığlıklarıyla ülkeden çıkardı.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Ulusların topraklarını verdi onlara. Halkların emeğini miras aldılar;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Kurallarını yerine getirsinler, Yasalarına uysunlar diye. RAB'be övgüler sunun!

< Psalms 105 >