< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Alabad al SEÑOR, invocad su Nombre; haced notorias sus obras en los pueblos.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Cantadle, decid salmos a él; hablad de todas sus maravillas.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Gloriaos en su Nombre santo; alégrese el corazón de los que buscan al SEÑOR.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Buscad al SEÑOR, y su fortaleza; buscad su rostro siempre.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Acordaos de sus maravillas que hizo, de sus prodigios y de los juicios de su boca,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
oh vosotros, simiente de Abraham su siervo, hijos de Jacob, sus escogidos.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
El es el SEÑOR nuestro Dios; en toda la tierra son sus juicios.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Se acordó para siempre de su alianza; de la palabra que mandó para mil generaciones,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
la cual concertó con Abraham; y de su juramento a Isaac.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Y la estableció a Jacob por decreto, a Israel por pacto eterno,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
diciendo: A ti te daré la tierra de Canaán por cordel de vuestra heredad.
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Esto siendo ellos pocos hombres en número, y extranjeros en ella.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Y anduvieron de gente en gente, de un reino a otro pueblo.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
No consintió que hombre los agraviase; y por causa de ellos castigó los reyes.
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Diciendo: No toquéis a mis ungidos, ni hagáis mal a mis profetas.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Y llamó al hambre sobre la tierra, y quebrantó toda fuerza de pan.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Envió un varón delante de ellos, a José, que fue vendido por siervo.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Afligieron sus pies con grillos; en hierro fue puesta su alma.
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Hasta la hora que llegó su palabra, el dicho del SEÑOR le purificó.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Envió el rey, y le soltó; el señor de los pueblos, y le desató.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Lo puso por señor de su casa, y por enseñoreador en toda su posesión;
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
para echar presos sus príncipes como él quisiese, y enseñó sabiduría a sus ancianos.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Después entró Israel en Egipto, y Jacob fue extranjero en la tierra de Cam.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Y multiplicó su pueblo en gran manera, y lo hizo más fuerte que sus enemigos.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Volvió el corazón de ellos para que aborreciesen a su pueblo, para que pensasen mal contra sus siervos.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Envió a su siervo Moisés, y a Aarón al cual escogió.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Puso en ellos las palabras de sus señales, y sus prodigios en la tierra de Cam.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Echó tinieblas, e hizo oscuridad; y no fueron rebeldes a su palabra.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Volvió sus aguas en sangre, y mató sus peces.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Engendró ranas su tierra, ranas en las camas de sus mismos reyes.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Dijo, y vinieron enjambres de moscas, y piojos en todo su término.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Volvió sus lluvias en granizo; en fuego de llamas en su tierra.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
E hirió sus viñas y sus higueras, y quebró los árboles de su término.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Dijo, y vinieron langostas, y pulgón sin número;
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
y comieron toda la hierba de su tierra, y comieron el fruto de su tierra.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Hirió además a todos los primogénitos en su tierra, el principio de toda su fuerza.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Y los sacó con plata y oro; y no hubo en sus tribus enfermo.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Egipto se alegró en su salida; porque había caído sobre ellos su terror.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Extendió una nube por cubierta, y fuego para alumbrar la noche.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Pidieron, e hizo venir codornices; y de pan del cielo los sació.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Abrió la peña, y corrieron aguas; fluyeron por los secadales un río.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Porque se acordó de su santa palabra con Abraham su siervo.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Y sacó a su pueblo con gozo; con júbilo a sus escogidos.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Y les dio las tierras de los gentiles; y las labores de las naciones heredaron,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
para que guardasen sus estatutos, y observasen sus leyes. Alelu-JAH.

< Psalms 105 >