< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Slavite Gospoda, razglasujte ime njegovo; med ljudstvi oznanjujte dejanja njegova.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Pojte mu, prepevajte mu, razgovarjajte se o vseh čudovitih delih njegovih.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Hvalite se v svetem imenu njegovem; veseli se naj srce njih, ki iščejo Gospoda.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Iščite Gospoda in moči njegove; iščite vedno njegovega obličja.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Spominjajte se čudovitih del njegovih, katera je storil; čudežev njegovih in sodbâ ust njegovih.
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
O seme Abrahama, njegovega hlapca; o izvoljeni sina njegovega Jakoba!
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Ta je Gospod, Bog naš, po vsej zemlji so sodbe njegove.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Spominja se vekomaj zaveze svoje, besede, katero je zapovedal na tisoč rodov,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Katero je sklenil z Abrahamom, in prisege svoje Izaku,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Katero je dal Jakobu v postavo; Izraelu v vedno zavezo.
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Govoreč: Tebi hočem dati deželo Kanaansko, vrvco posesti vaše.
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Dasí je bilo ljudî malo, prav malo, in tujci v njej,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
In so hodili od naroda do naroda, iz kraljestva k drugemu ljudstvu;
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Ni dovolil zatíratí jih nikomur; dà, strahoval je zavolje njih kralje:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Ne dotaknite se maziljencev mojih, in ne storite žalega prerokom."
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Ko je bil poklical lakot nad deželo, in kruhu strl vso podporo;
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Poslal je bil moža pred njimi odličnega; kateri je bil v sužnjost prodan, Jožefa.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Noge njegove so vklenili z vezjo, v železo se je on podal.
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Noter do časa, ko je imela priti beseda njegova; govor Gospodov ga je potrdil.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Poslal je kralj in velel ga razvezati; in poglavar ljudstev ga je oprostil.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Postavil ga je za gospoda družini svoji, in za poglavarja vsej svoji posesti,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Da bi zvezaval kneze po volji svoji, in podučeval njih starejšine.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Nato je prišel Izrael v Egipt, in Jakob je tujčeval po deželi Kamovi.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Ko je bil tam storil Bog, da je bilo ljudstvo njegovo silno rodovitno, in ga je bil močnejšega naredil od sovražnikov njegovih,
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Izpremenil je njih srce, da so sovražili ljudstvo njegovo, da so naklepe delali zoper hlapce njegove.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Poslal je Mojzesa, hlapca svojega, Arona, katerega je bil izvolil.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Razlagala sta pred njimi besede znamenj njegovih, in čudežev v deželi Kamovi.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Poslal je temé, in otemnile so jo, in upirala se niso znamenja zoper besedo njegovo.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Izpremenil je bil v kri njih vodé, in pokončal je bil njih ribe.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Obilo je rodila njih dežela žab, ki so napadle kraljev samih stanice.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Ko je izrekel, prišlo je krdelo živali; uši na vso njih pokrajino.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Dež jim je naredil v točo, ogenj silno plameneč v njih kraji.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
S tem je zadel njih trte in njih smokve, in polomil njih pokrajine drevesa.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Ko je izrekel, prišla je kobilica in hrošč, in ta brez števila.
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
On je požrl vso travo njih kraja, in požrl sad njih dežele.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Slednjič je udaril vse prvorojeno v njih kraji; prvino vse njih moči.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Tedaj jih je izpeljal sè srebrom in zlatom, in ni ga bilo, da bi pešal, med njih rodovi.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Veselili so se Egipčani, ko so izhajali tí; ker njih strah jih je bil obšel.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Razgrnil je oblak za odejo, in ogenj, da je noč razsvetljeval.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Prosili so, in poslal jim je prepelic, in s kruhom nebeškim jih je sitil.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
In odprl je skalo, in pritekle so vode, ter šle so po suhih krajih, kakor reka.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Ker se je spominjal besede svetosti svoje, z Abrahamom, hlapcem svojim.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Zató je izpeljal ljudstvo svoje, z veseljem, s petjem izvoljene svoje.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
In dal jim je kraje narodov, in delo ljudstev so posedli;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Da se držé postav njegovih, in hranijo zakone njegove.

< Psalms 105 >