< Psalms 105 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Aduceți mulțumiri DOMNULUI; chemați numele lui, faceți cunoscute faptele lui printre popoare.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Cântați-i, cântați-i psalmi, vorbiți despre toate lucrările lui minunate.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Lăudați-vă în sfântul său nume, să se bucure inima celor ce caută pe DOMNUL.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Căutați pe DOMNUL și puterea lui, căutați fața lui întotdeauna.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Amintiți-vă lucrările lui minunate pe care le-a făcut, minunile lui și judecățile gurii sale,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Voi, sămânță a lui Avraam, servitorul lui, copii ai lui Iacob, aleșii lui.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
El este DOMNUL Dumnezeul nostru, judecățile lui sunt pe tot pământul.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
El și-a amintit legământul său pentru totdeauna, cuvântul care l-a poruncit la o mie de generații.
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Legământ pe care l-a făcut cu Avraam și jurământul său lui Isaac;
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Și a confirmat același legământ lui Iacob ca lege, și lui Israel ca legământ veșnic,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Spunând: Ție îți voi da țara Canaanului, sorțul moștenirii tale;
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Când au fost doar puțini oameni la număr; da, foarte puțini și străini în ea.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Când au mers de la o națiune la alta, de la o împărăție la alt popor;
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
El nu a permis niciunui om să le facă rău; da, a mustrat împărați pentru ei,
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Spunând: Nu atingeți pe unșii mei și nu faceți rău profeților mei.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Mai mult, a chemat foamete peste țară, a frânt tot toiagul pâinii.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
A trimis un om înaintea lor, pe Iosif, care a fost vândut ca servitor,
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Ale cărui picioare le-au rănit cu cătușe, fiind pus în fiare,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Până la timpul când cuvântul său a venit, cuvântul DOMNULUI l-a încercat.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Împăratul, stăpânul poporului, a trimis și l-a dezlegat și l-a eliberat.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
L-a făcut domn al casei sale și stăpân peste toată averea sa,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Pentru a lega pe prinții lui după plăcerea sa și a învăța pe bătrânii săi înțelepciune.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Israel de asemenea a venit în Egipt; și Iacob a locuit temporar în țara lui Ham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Și el a înmulțit mult pe poporul lui; și i-a făcut mai puternici decât pe dușmanii lor.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
A întors inima lor pentru a urî pe poporul său, ca să se poarte cu viclenie cu servitorii săi.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
A trimis pe Moise, servitorul său; și pe Aaron, pe care l-a ales.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ei au arătat semnele lui printre ei și minuni în țara lui Ham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
El a trimis întunecime și a făcut-o întuneric; și nu s-au răzvrătit împotriva cuvântului său.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Le-a prefăcut apele în sânge și le-a ucis peștii.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Pământul lor a adus broaște din abundență, în încăperile împăraților lor.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
El a vorbit și au venit multe feluri de muște și păduchi în toate ținuturile lor.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Le-a dat grindină ca ploaie și flăcări de foc în țara lor.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
A lovit de asemenea viile lor și smochinii lor și a rupt copacii din ținuturile lor.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
El a vorbit și lăcustele și omizile au venit fără număr,
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Și au mâncat toată verdeața în țara lor și au mâncat rodul pământului lor.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
A lovit de asemenea toți întâii născuți în țara lor, măreția întregii lor puteri.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
De asemenea i-a scos afară cu argint și aur; și nu a fost nimeni fără vlagă printre triburile lor.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Egiptul s-a veselit la plecarea lor, căci spaima de ei a căzut asupra lor.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
El a întins un nor ca acoperitoare și foc pentru a da lumină în timpul nopții.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Poporul a cerut și el a adus prepelițe și i-a săturat cu pâinea cerului.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
El a deschis stânca și apele au țâșnit; ele au alergat în locurile uscate ca un râu.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Căci și-a amintit promisiunea sa sfântă și de Avraam servitorul său.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Și și-a adus afară poporul cu bucurie și pe aleșii săi cu veselie;
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Și le-a dat țările păgânilor și au moștenit munca popoarelor;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Ca să păzească statutele lui și să țină legile lui. Lăudați pe DOMNUL.