< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Mwebaze Mukama, mukoowoole erinnya lye; amawanga gonna mugategeeze by’akoze.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Mumuyimbire, mumutendereze; muyimbe ku byamagero bye.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Mumusuute, ng’erinnya lye ettukuvu muligulumiza; emitima gy’abo abanoonya Mukama gijjule essanyu.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Munoonye Mukama n’amaanyi ge; mumunoonyenga ennaku zonna.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Mujjukirenga eby’ekitalo bye yakola, ebyamagero bye, n’emisango gye yasala;
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
mmwe abazzukulu ba Ibulayimu, abaweereza be mmwe abaana ba Yakobo, abalonde be.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Ye Mukama Katonda waffe; ye alamula mu nsi yonna.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Ajjukira endagaano ye emirembe gyonna, kye kigambo kye yalagira, ekyakamala emirembe olukumi,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
ye ndagaano gye yakola ne Ibulayimu, era kye kisuubizo kye yalayirira Isaaka.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Yakikakasa Yakobo ng’etteeka, n’akiwa Isirayiri ng’endagaano eteriggwaawo nti,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
“Ndikuwa ggwe ensi ya Kanani okuba omugabo gwo.”
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Bwe baali bakyali batono, nga si bangi n’akamu, era nga bagwira mu nsi omwo,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
baatambulatambulanga okuva mu ggwanga erimu okulaga mu ddala, ne bavanga mu bwakabaka obumu ne balaga mu bulala.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Teyaganya muntu yenna kubayisa bubi; n’alabulanga bakabaka ku lwabwe nti,
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
“Abalonde bange, ne bannabbi bange temubakolangako kabi.”
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Yaleeta enjala mu nsi, emmere yaabwe yonna n’agizikiriza.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
N’atuma omuntu okubeesooka mu maaso, ye Yusufu eyatundibwa ng’omuddu,
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
ebigere bye ne binuubulwa enjegere ze baamusibya, obulago bwe ne buteekebwa mu byuma,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
okutuusa bye yategeeza lwe byatuukirira, okutuusa ekigambo kya Mukama lwe kyamukakasa nti bye yayogera bya mazima.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Kabaka n’atuma ne bamusumulula; omufuzi w’ensi eyo yamuggya mu kkomera.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Yamufuula omukulu w’eby’omu maka ge, n’akulira byonna omufuzi oyo bye yalina;
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
okukangavvulanga abalangira be nga bwe yalabanga, n’okuyigiriza abakulu eby’amagezi.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Oluvannyuma Isirayiri n’ajja mu Misiri; Yakobo bw’atyo n’atuula mu nsi ya Kaamu nga munnaggwanga.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Mukama n’ayaza nnyo abantu be; ne baba bangi nnyo, n’abalabe baabwe ne beeraliikirira,
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
n’akyusa emitima gyabwe ne bakyawa abantu be, ne basalira abaweereza be enkwe.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Yatuma abaweereza be Musa ne Alooni, be yalonda.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ne bakola obubonero bwe obw’ekitalo mu bantu abo; ne bakolera ebyamagero bye mu nsi ya Kaamu.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Yaleeta ekizikiza ensi yonna n’ekwata, kubanga baali bajeemedde ekigambo kye.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Amazzi gaabwe yagafuula omusaayi, ne kireetera ebyennyanja byabwe okufa.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Ensi yaabwe yajjula ebikere, ebyatuukira ddala ne mu bisenge by’abafuzi baabwe.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Yalagira, ebiwuka ebya buli ngeri ne bijja, n’ensekere ne zeeyiwa mu bitundu byonna eby’ensi yaabwe.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Yafuula enkuba okuba amayinja g’omuzira; eggulu ne libwatuka mu nsi yaabwe yonna.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Yakuba emizeeyituuni n’emizabbibu, n’azikiriza emiti gy’omu nsi yaabwe.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Yalagira, enzige ne zijja ne bulusejjera obutabalika muwendo.
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Ne birya buli kimera kyonna mu nsi yaabwe, na buli kisimbe kyonna mu ttaka lyabwe ne kiriibwa.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
N’azikiriza abaana ababereberye bonna mu nsi yaabwe, nga bye bibala ebisooka eby’obuvubuka bwabwe.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Yaggya Abayisirayiri mu nsi eyo nga balina ffeeza nnyingi ne zaabu; era bonna baali ba maanyi.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Abamisiri baasanyuka bwe baalaba Abayisirayiri nga bagenze, kubanga baali batandise okubatiira ddala.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Yayanjuluzanga ekire ne kibabikka, n’omuliro ne gubamulisiza ekiro.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Baamusaba, n’abaweereza enkwale era n’abaliisanga emmere eva mu ggulu ne bakkuta.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Yayasa olwazi, amazzi ne gatiiriika, ne gakulukuta mu ddungu ng’omugga.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Kubanga yajjukira ekisuubizo kye ekitukuvu kye yawa omuweereza we Ibulayimu.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Abantu be yabaggyayo nga bajaguza, abalonde be nga bayimba olw’essanyu.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Yabawa ensi eyali ey’amawanga amalala, ne basikira ebyo abalala bye baakolerera;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
balyoke bakwatenga amateeka ge, era bagonderenga ebiragiro bye. Mumutendereze Mukama.

< Psalms 105 >