< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Pateiciet Tam Kungam, piesauciet Viņa Vārdu, dariet zināmus starp tiem ļaudīm Viņa darbus.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Dziediet Viņam, slavējiet Viņu ar dziesmām, pārdomājiet visus Viņa brīnumus.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Slavējiet Viņa svēto vārdu; lai tās sirdis priecājās, kas To Kungu meklē.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Vaicājiet pēc Tā Kunga un pēc Viņa spēka, meklējiet vienmēr Viņa vaigu.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Pieminiet Viņa brīnumus, ko Viņš ir darījis, Viņa brīnuma darbus un Viņa mutes tiesas, -
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Tu Ābrahāma, Viņa kalpa dzimums, jūs Jēkaba bērni, Dieva izredzētie!
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Viņš ir Tas Kungs, mūsu Dievs; Viņa tiesas iet pār visu zemi.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Viņš piemin Savu derību mūžam, to vārdu, ko Viņš ir iecēlis tūkstošiem dzimumiem,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Ko Viņš ar Ābrahāmu derējis un ko zvērējis Īzakam.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
To Viņš arī Jēkabam ir iecēlis par likumu, Israēlim par mūžīgu derību,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Sacīdams: tev Es došu Kanaāna zemi, jūsu mantības daļu;
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Kad tie vēl bija mazs pulciņš, ne daudz, un svešinieki iekš tās,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Un staigāja no vienas tautas pie otras, no vienas valsts pie otras valsts ļaudīm,
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Viņš nevienam neļāva tos apbēdināt, Viņš arī ķēniņus sodīja viņu dēļ:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Neaizskariet Manus svaidītos un nedariet ļauna Maniem praviešiem!
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Viņš aicināja badu pār zemi, Viņš atņēma visu maizes padomu.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Viņš sūtīja viņu priekšā vienu vīru; Jāzeps tapa pārdots par kalpu.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Viņa kājas tapa spaidītas siekstā, viņa miesas nāca dzelzīs,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Tiekams viņa vārds notika, un Tā Kunga sludinājums to pārbaudīja.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Tas ķēniņš sūtīja un lika to atraisīt, tas ļaužu valdītājs to atlaida vaļā.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Viņš to iecēla par kungu savam namam un par valdnieku visai savai mantai.
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Ka tas saistītu viņa lielkungus pēc sava prāta un mācītu gudrību viņa vecākajiem.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Tā Israēls nāca Ēģiptes zemē un Jēkabs piemita Hama zemē.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Un Viņš Saviem ļaudīm lika augumā augt un tos darīja jo varenus nekā viņu pretiniekus.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Viņš pārvērsa viņu sirdi, ienīdēt Viņa ļaudis un ar viltu glūnēt uz Viņa kalpiem.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Viņš sūtīja Mozu, Savu kalpu, un Āronu, ko Viņš bija izredzējis.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Tie darīja viņu starpā Dieva brīnumus un brīnuma zīmes Hama zemē.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Viņš sūtīja tumsu, tad kļuva tumšs; un tie Viņa Vārdam neturējās pretī.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Viņš pārvērsa viņu ūdeņus par asinīm un nokāva viņu zivis.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Viņu zeme mudžēja no vardēm viņu ķēniņu kambaros.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Viņš runāja, tad nāca kukaiņi, utis visās viņu robežās.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Viņš tiem deva krusu lietus vietā, uguns liesmas viņu zemē,
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Un sasita viņu vīna kokus un viņu vīģes kokus un salauzīja kokus viņu robežās.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Viņš runāja, tad nāca siseņi un vaboles neizskaitāmā pulkā,
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Kas apēda visu zāli viņu zemē, un norija viņu zemes augļus.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Viņš kāva arī visus pirmdzimtos viņu zemē un visu viņu pirmo stiprumu.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Un tos izveda ar sudrabu un zeltu, un neviena gurdena nebija viņu ciltīs.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Ēģiptes zeme priecājās, kad tie izgāja, jo viņu bailes uz tiem bija kritušas.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Viņš deva padebesi par apsegu, un uguni naktī par gaismu.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Tie lūdza un viņš lika nākt paipalām un tos ēdināja ar debes'maizi.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Viņš pāršķēla klinti, tad ūdens iztecēja, un upes skrēja tuksnesī.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Jo Viņš pieminēja Savu svēto vārdu un Ābrahāmu, Savu kalpu.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Tā Viņš izveda Savus ļaudis ar prieku un Savus izredzētos ar gavilēšanu,
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Un tiem deva pagānu zemes; tie iemantoja tautu sviedrus,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Lai turētu Viņa likumus un sargātu Viņa bauslību. Alleluja.

< Psalms 105 >