< Psalms 105 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
alleluia confitemini Domino et invocate nomen eius adnuntiate inter gentes opera eius
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
cantate ei et psallite ei narrate omnia mirabilia eius
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
laudamini in nomine sancto eius laetetur cor quaerentium Dominum
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
quaerite Dominum et confirmamini quaerite faciem eius semper
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
mementote mirabilium eius quae fecit prodigia eius et iudicia oris eius
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
semen Abraham servi eius filii Iacob electi eius
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
ipse Dominus Deus noster in universa terra iudicia eius
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
memor fuit in saeculum testamenti sui verbi quod mandavit in mille generationes
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
quod disposuit ad Abraham et iuramenti sui ad Isaac
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
et statuit illud Iacob in praeceptum et Israhel in testamentum aeternum
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
dicens tibi dabo terram Chanaan funiculum hereditatis vestrae
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
cum essent numero breves paucissimos et incolas eius
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
et pertransierunt de gente in gentem et de regno ad populum alterum
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
non reliquit hominem nocere eis et corripuit pro eis reges
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
nolite tangere christos meos et in prophetis meis nolite malignari
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
et vocavit famem super terram omne firmamentum panis contrivit
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
misit ante eos virum in servum venundatus est Ioseph
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
humiliaverunt in conpedibus pedes eius ferrum pertransiit anima eius
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
donec veniret verbum eius eloquium Domini inflammavit eum
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
misit rex et solvit eum princeps populorum et dimisit eum
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
constituit eum dominum domus suae et principem omnis possessionis suae
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
ut erudiret principes eius sicut semet ipsum et senes eius prudentiam doceret
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
et intravit Israhel in Aegyptum et Iacob accola fuit in terra Cham
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
et auxit populum eius vehementer et firmavit eum super inimicos eius
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
convertit cor eorum ut odirent populum eius ut dolum facerent in servos eius
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
misit Mosen servum suum Aaron quem elegit ipsum
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
posuit in eis verba signorum suorum et prodigiorum in terra Cham
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
misit tenebras et obscuravit et non exacerbavit sermones suos
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
convertit aquas eorum in sanguinem et occidit pisces eorum
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
dedit terra eorum ranas in penetrabilibus regum ipsorum
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
dixit et venit cynomia et scinifes in omnibus finibus eorum
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
posuit pluvias eorum grandinem ignem conburentem in terra ipsorum
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
et percussit vineas eorum et ficulneas eorum et contrivit lignum finium eorum
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
dixit et venit lucusta et bruchus cuius non erat numerus
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
et comedit omne faenum in terra eorum et comedit omnem fructum terrae eorum
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
et percussit omne primogenitum in terra eorum primitias omnis laboris eorum
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
et eduxit eos in argento et auro et non erat in tribubus eorum infirmus
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
laetata est Aegyptus in profectione eorum quia incubuit timor eorum super eos
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
expandit nubem in protectionem eorum et ignem ut luceret eis per noctem
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
petierunt et venit coturnix et panem caeli saturavit eos
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
disrupit petram et fluxerunt aquae abierunt in sicco flumina
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
quoniam memor fuit verbi sancti sui quod habuit ad Abraham puerum suum
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
et eduxit populum suum in exultatione et electos suos in laetitia
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
et dedit illis regiones gentium et labores populorum possederunt
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
ut custodiant iustificationes eius et legem eius requirant