< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Alleluia. Confitemini Domino, et invocate nomen eius: annunciate inter gentes opera eius.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Cantate ei, et psallite ei: narrate omnia mirabilia eius.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Laudamini in nomine sancto eius: laetetur cor quaerentium Dominum.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Quaerite Dominum, et confirmamini: quaerite faciem eius semper.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Mementote mirabilium eius, quae fecit: prodigia eius, et iudicia oris eius.
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Semen Abraham, servi eius: filii Iacob electi eius.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Ipse Dominus Deus noster: in universa terra iudicia eius.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Memor fuit in saeculum testamenti sui: verbi, quod mandavit in mille generationes:
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Quod disposuit ad Abraham: et iuramenti sui ad Isaac:
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Et statuit illud Iacob in praeceptum: et Israel in testamentum aeternum:
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Dicens: Tibi dabo Terram Chanaan, funiculum hereditatis vestrae.
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Cum essent numero brevi, paucissimi et incolae eius:
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Et pertransierunt de gente in gentem, et de regno ad populum alterum.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Non reliquit hominem nocere eis: et corripuit pro eis reges.
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Nolite tangere christos meos: et in prophetis meis nolite malignari.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Et vocavit famem super terram: et omne firmamentum panis contrivit.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Misit ante eos virum: in servum venundatus est Ioseph.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Humiliaverunt in compedibus pedes eius, ferrum pertransiit animam eius,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
donec veniret verbum eius. Eloquium Domini inflammavit eum:
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
misit rex, et solvit eum; princeps populorum, et dimisit eum.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Constituit eum dominum domus suae: et principem omnis possessionis suae:
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Ut erudiret principes eius sicut semetipsum: et senes eius prudentiam doceret.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Et intravit Israel in Aegyptum: et Iacob accola fuit in Terra Cham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Et auxit populum suum vehementer: et firmavit eum super inimicos eius.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Convertit cor eorum ut odirent populum eius: et dolum facerent in servos eius.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Misit Moysen servum suum: Aaron, quem elegit ipsum.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Posuit in eis verba signorum suorum, et prodigiorum in Terra Cham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Misit tenebras, et obscuravit: et non exacerbavit sermones suos.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Convertit aquas eorum in sanguinem: et occidit pisces eorum.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Edidit terra eorum ranas in penetralibus regum ipsorum.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Dixit, et venit cynomyia: et cinifes in omnibus finibus eorum.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Posuit pluvias eorum grandinem: ignem comburentem in terra ipsorum.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Et percussit vineas eorum, et ficulneas eorum: et contrivit lignum finium eorum.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Dixit, et venit locusta, et bruchus, cuius non erat numerus:
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Et comedit omne foenum in terra eorum: et comedit omnem fructum terrae eorum.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Et percussit omne primogenitum in terra eorum: primitias omnis laboris eorum.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Et eduxit eos cum argento et auro: et non erat in tribubus eorum infirmus.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Laetata est Aegyptus in profectione eorum: quia incubuit timor eorum super eos.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Expandit nubem in protectionem eorum, et ignem ut luceret eis per noctem.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Petierunt, et venit coturnix: et pane caeli saturavit eos.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Dirupit petram, et fluxerunt aquae: abierunt in sicco flumina;
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Quoniam memor fuit verbi sancti sui, quod habuit ad Abraham puerum suum.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Et eduxit populum suum in exultatione, et electos suos in laetitia.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Et dedit illis regiones gentium: et labores populorum possederunt:
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Ut custodiant iustificationes eius, et legem eius requirant.

< Psalms 105 >