< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
הודו ליהוה קראו בשמו הודיעו בעמים עלילותיו׃
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
שירו לו זמרו לו שיחו בכל נפלאותיו׃
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
התהללו בשם קדשו ישמח לב מבקשי יהוה׃
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
דרשו יהוה ועזו בקשו פניו תמיד׃
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
זכרו נפלאותיו אשר עשה מפתיו ומשפטי פיו׃
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
זרע אברהם עבדו בני יעקב בחיריו׃
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
הוא יהוה אלהינו בכל הארץ משפטיו׃
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
זכר לעולם בריתו דבר צוה לאלף דור׃
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
אשר כרת את אברהם ושבועתו לישחק׃
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
ויעמידה ליעקב לחק לישראל ברית עולם׃
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
לאמר לך אתן את ארץ כנען חבל נחלתכם׃
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
בהיותם מתי מספר כמעט וגרים בה׃
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
ויתהלכו מגוי אל גוי מממלכה אל עם אחר׃
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
לא הניח אדם לעשקם ויוכח עליהם מלכים׃
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
אל תגעו במשיחי ולנביאי אל תרעו׃
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
ויקרא רעב על הארץ כל מטה לחם שבר׃
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
שלח לפניהם איש לעבד נמכר יוסף׃
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
ענו בכבל רגליו ברזל באה נפשו׃
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
עד עת בא דברו אמרת יהוה צרפתהו׃
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
שלח מלך ויתירהו משל עמים ויפתחהו׃
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
שמו אדון לביתו ומשל בכל קנינו׃
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
לאסר שריו בנפשו וזקניו יחכם׃
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
ויבא ישראל מצרים ויעקב גר בארץ חם׃
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
ויפר את עמו מאד ויעצמהו מצריו׃
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
הפך לבם לשנא עמו להתנכל בעבדיו׃
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
שלח משה עבדו אהרן אשר בחר בו׃
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
שמו בם דברי אתותיו ומפתים בארץ חם׃
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
שלח חשך ויחשך ולא מרו את דבריו׃
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
הפך את מימיהם לדם וימת את דגתם׃
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
שרץ ארצם צפרדעים בחדרי מלכיהם׃
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
אמר ויבא ערב כנים בכל גבולם׃
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
נתן גשמיהם ברד אש להבות בארצם׃
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
ויך גפנם ותאנתם וישבר עץ גבולם׃
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
אמר ויבא ארבה וילק ואין מספר׃
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
ויאכל כל עשב בארצם ויאכל פרי אדמתם׃
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
ויך כל בכור בארצם ראשית לכל אונם׃
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
ויוציאם בכסף וזהב ואין בשבטיו כושל׃
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
שמח מצרים בצאתם כי נפל פחדם עליהם׃
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
פרש ענן למסך ואש להאיר לילה׃
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
שאל ויבא שלו ולחם שמים ישביעם׃
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
פתח צור ויזובו מים הלכו בציות נהר׃
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
כי זכר את דבר קדשו את אברהם עבדו׃
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
ויוצא עמו בששון ברנה את בחיריו׃
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
ויתן להם ארצות גוים ועמל לאמים יירשו׃
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
בעבור ישמרו חקיו ותורתיו ינצרו הללו יה׃

< Psalms 105 >