< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Célébrez l'Éternel, invoquez son nom; Faites connaître parmi les nations ses grandes oeuvres!
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Chantez, psalmodiez en son honneur; Parlez de toutes ses merveilles!
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Glorifiez-vous de son saint nom; Que ceux dont le coeur recherche l'Éternel se réjouissent!
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Implorez l'Éternel et son puissant secours; Recherchez continuellement sa présence!
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Souvenez-vous des merveilles qu'il a faites, De ses miracles, et des jugements que sa bouche a prononcés,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
vous, descendants d'Abraham, son serviteur, Enfants de Jacob, ses élus!
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
C'est lui, l'Éternel, qui est notre Dieu; Ses jugements s'exercent sur toute la terre.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Il se souvient à jamais de son alliance, De la parole qu'il a donnée pour mille générations,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
De la promesse qu'il a faite à Abraham, Du serment qu'il a fait à Isaac,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Et qu'il a confirmé à Jacob comme une loi, A Israël comme une alliance éternelle,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
En disant: «Je te donnerai le pays de Canaan; C'est là votre part d'héritage.»
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Ils n'étaient alors qu'une poignée d'hommes. Peu nombreux et étrangers dans le pays,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Allant de nation en nation. Et d'un royaume à un autre.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
L'Éternel ne permit à personne de les opprimer; Il châtia des rois à cause d'eux:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
«Ne touchez pas à ceux que j'ai oints, dit-il. Et ne faites pas de mal à mes prophètes!»
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Il appela sur la terre la famine, Et priva son peuple de toute subsistance.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Il envoya un homme pour précéder Israël: Joseph fut vendu comme esclave.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
On lui serra les pieds dans des entraves, Et il fut jeté dans les fers,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Jusqu'au jour où ce qu'il avait dit arriva, Et où la parole de l'Eternel montra ce qu'il était.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Alors le roi envoya délivrer Joseph; Le dominateur des peuples le fit élargir.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Il l'établit seigneur de sa maison Et gouverneur de tous ses biens,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Pour commander en maître à ses princes Et enseigner à ses anciens la sagesse.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Alors Israël vint en Egypte; Jacob séjourna dans le pays de Cham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Dieu multiplia son peuple d'une façon prodigieuse, Et le rendit plus puissant que ses oppresseurs.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Puis il changea le coeur des Égyptiens, qui haïrent son peuple Et traitèrent avec perfidie ses serviteurs.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Il envoya Moïse, son serviteur, Et Aaron qu'il avait élu.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Sur son ordre, ils accomplirent au milieu d'eux des prodiges Et des miracles dans le pays de Cham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Ils firent surgir les ténèbres de la nuit, Pour ne pas désobéir à sa parole.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Dieu changea, leurs fleuves en sang. Et il en fit mourir les poissons.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Leur terre fourmilla de grenouilles. Jusque dans les chambres de leurs rois.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Il dit; et l'on vit paraître des insectes. Des moustiques, dans tout leur territoire.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Au lieu de pluie, il leur envoya de la grêle. Et des flammes de feu dans tout leur pays.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Il frappa leurs vignes et leurs figuiers, Et il mit en pièces les arbres de leur territoire.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Il dit; et l'on vit des sauterelles, Des criquets sans nombre,
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Qui dévorèrent toute l'herbe de leurs champs, Qui ravagèrent les fruits de leur sol.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Il frappa dans leur pays tous les premiers-nés, Prémices de leur virilité.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Puis Dieu fit sortir les Israélites, chargés d'argent et d'or. Et aucun d'eux, parmi les tribus, ne resta en arrière.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Les Égyptiens se réjouirent de leur départ; Car la frayeur s'était emparée d'eux.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
L'Éternel étendit la nuée pour couvrir les enfants d'Israël, Ainsi que la colonne de feu pour les éclairer pendant la nuit.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
A leur demande, il fit venir des cailles, Et il les rassasia du pain des cieux.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Il ouvrit le rocher, et les eaux en jaillirent: Elles coulèrent à travers le désert, comme un fleuve;
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Car il se souvenait de sa parole sainte. Et d'Abraham, son serviteur.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Il fit avancer son peuple au milieu des cris d'allégresse, Et ses élus au milieu des chants de triomphe.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Il leur donna les terres des nations, Et il leur abandonna les fruits du labeur des peuples,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
A condition qu'ils garderaient ses commandements Et pratiqueraient ses lois. Louez l'Éternel!

< Psalms 105 >