< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Célébrez l'Éternel; invoquez son nom; faites connaître parmi les peuples ses hauts faits!
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Chantez-lui, psalmodiez-lui; parlez de toutes ses merveilles!
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Glorifiez-vous de son saint nom; que le cœur de ceux qui cherchent l'Éternel se réjouisse!
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Recherchez l'Éternel et sa force; cherchez continuellement sa face!
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Souvenez-vous des merveilles qu'il a faites, de ses miracles et des jugements de sa bouche;
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Vous, postérité d'Abraham, son serviteur, enfants de Jacob, ses élus!
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
C'est lui, l'Éternel, qui est notre Dieu; ses jugements sont sur toute la terre.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Il se souvient à jamais de son alliance, de sa promesse établie pour mille générations;
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Du traité qu'il fit avec Abraham, et du serment qu'il fit à Isaac,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Et qu'il a confirmé à Jacob pour être un statut, à Israël pour être une alliance éternelle,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Disant: Je te donnerai le pays de Canaan; c'est le lot de votre héritage;
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Lorsqu'ils n'étaient qu'une poignée de gens, peu nombreux et étrangers dans le pays,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Allant de nation en nation, et d'un royaume vers un autre royaume.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Il ne permit à personne de les opprimer, et il châtia des rois à cause d'eux,
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Disant: Ne touchez pas à mes oints, et ne faites point de mal à mes prophètes!
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Il appela sur la terre la famine, et rompit tout l'appui du pain.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
II envoya devant eux un homme; Joseph fut vendu comme esclave.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
On lui serra les pieds dans des ceps, et sa vie fut mise dans les fers;
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Jusqu'au temps où ce qu'il avait dit arriva, où la parole de l'Éternel le fit connaître.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Le roi l'envoya délivrer; le dominateur des peuples le fit élargir.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Il l'établit seigneur de sa maison, et gouverneur de tous ses biens;
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Pour enchaîner à son gré ses princes, et enseigner à ses anciens la sagesse.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Alors Israël vint en Égypte; Jacob séjourna au pays de Cham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Dieu fit fort multiplier son peuple, et le rendit plus puissant que ses oppresseurs.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Puis il changea leur cœur, tellement qu'ils haïrent son peuple, et agirent perfidement contre ses serviteurs.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Il envoya Moïse, son serviteur, Aaron qu'il avait élu.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ils opérèrent au milieu d'eux ses prodiges, et des miracles dans le pays de Cham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Il envoya des ténèbres, et produisit l'obscurité; et ils ne furent pas rebelles à sa parole.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Il changea leurs eaux en sang, et fit mourir leurs poissons.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Leur terre fourmilla de grenouilles, jusque dans les chambres de leurs rois.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Il parla, et des insectes vinrent, des moucherons dans tout leur territoire.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Il leur donna pour pluie de la grêle, des flammes de feu sur leur pays.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Il frappa leurs vignes et leurs figuiers, et brisa les arbres de leur territoire.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Il parla, et des sauterelles vinrent, des insectes rongeurs sans nombre,
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Qui dévorèrent toute l'herbe de leur pays, qui dévorèrent les fruits de leurs champs.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Il frappa tous les premiers-nés dans leur pays, toutes les prémices de leur force.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Puis il les fit sortir avec de l'argent et de l'or; et dans leurs tribus il n'y eut personne qui chancelât.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
L'Égypte se réjouit à leur départ, car la frayeur d'Israël les avait saisis.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Il étendit la nuée pour les couvrir, et le feu pour les éclairer de nuit.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
A leur demande, il fit venir des cailles; et il les rassasia du pain des cieux.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Il ouvrit le rocher, et les eaux coulèrent; elles coururent, par les lieux secs, comme un fleuve.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Car il se souvenait de sa parole sainte, et d'Abraham, son serviteur.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Et il fit sortir son peuple avec allégresse, ses élus avec des chants de joie.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Il leur donna les terres des nations, et ils possédèrent le travail des peuples;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Afin qu'ils gardassent ses ordonnances, et qu'ils observassent ses lois. Louez l'Éternel!

< Psalms 105 >