< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Célébrez l’Éternel, invoquez son nom; faites connaître parmi les peuples ses actes!
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Chantez-lui, chantez-lui des cantiques! Méditez toutes ses œuvres merveilleuses.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Glorifiez-vous de son saint nom; que le cœur de ceux qui cherchent l’Éternel se réjouisse!
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Recherchez l’Éternel et sa force, cherchez continuellement sa face;
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Souvenez-vous de ses œuvres merveilleuses qu’il a faites, de ses prodiges, et des jugements de sa bouche,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Vous, semence d’Abraham, son serviteur; vous, fils de Jacob, ses élus.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Lui, l’Éternel, est notre Dieu; ses jugements sont en toute la terre.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Il s’est souvenu pour toujours de son alliance, de la parole qu’il commanda pour mille générations,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
[De l’alliance] qu’il a faite avec Abraham, et qu’il a jurée à Isaac,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Et qu’il a établie pour Jacob comme statut, pour Israël comme alliance perpétuelle,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Disant: Je te donnerai le pays de Canaan, le lot de votre héritage;
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Quand ils étaient un petit nombre d’hommes, peu de chose, et étrangers dans le [pays],
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Et allant de nation en nation, d’un royaume vers un autre peuple.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Il ne permit à personne de les opprimer, et il reprit des rois à cause d’eux,
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
[Disant]: Ne touchez pas à mes oints, et ne faites pas de mal à mes prophètes.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Et il appela la famine sur la terre; il brisa tout le bâton du pain.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Il envoya un homme devant eux: Joseph fut vendu pour être esclave.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
On lui serra les pieds dans les ceps, son âme entra dans les fers,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Jusqu’au temps où arriva ce qu’il avait dit: la parole de l’Éternel l’éprouva.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Le roi envoya, et il le mit en liberté; le dominateur des peuples le relâcha.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Il l’établit seigneur sur sa maison, et gouverneur sur toutes ses possessions,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Pour lier ses princes à son plaisir, et pour rendre sages ses anciens.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Alors Israël entra en Égypte, et Jacob séjourna dans le pays de Cham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Et [l’Éternel] fit beaucoup multiplier son peuple, et le rendit plus puissant que ses oppresseurs.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Il changea leur cœur pour qu’ils haïssent son peuple, pour qu’ils complotent contre ses serviteurs.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Il envoya Moïse, son serviteur, Aaron qu’il avait choisi.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ils opérèrent au milieu d’eux ses signes, et des prodiges dans le pays de Cham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Il envoya des ténèbres, et fit une obscurité; et ils ne se rebellèrent pas contre sa parole.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Il changea leurs eaux en sang, et fit mourir leurs poissons.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Leur terre fourmilla de grenouilles, [jusque] dans les chambres de leurs rois.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Il parla, et il vint des mouches venimeuses, [et] des moustiques dans tous leurs confins.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Il leur donna pour pluie de la grêle, un feu de flammes dans leur pays;
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Et il frappa leurs vignes et leurs figuiers, et brisa les arbres de leur contrée.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Il parla, et les sauterelles vinrent, et des yéleks sans nombre;
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
Et ils dévorèrent toutes les plantes dans leur pays, et dévorèrent le fruit de leur sol.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Et il frappa tout premier-né dans leur pays, les prémices de toute leur vigueur.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Et il les fit sortir avec de l’argent et de l’or, et il n’y eut aucun infirme dans ses tribus.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
L’Égypte se réjouit à leur sortie, car la frayeur d’Israël était tombée sur eux.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Il étendit une nuée pour couverture, et un feu pour éclairer de nuit.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
Ils demandèrent, et il fit venir des cailles, et il les rassasia du pain des cieux.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Il ouvrit le rocher, et les eaux en découlèrent; elles allèrent par les lieux secs, comme une rivière.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Car il se souvint de sa parole sainte, [et] d’Abraham, son serviteur.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Et il fit sortir son peuple avec joie, ses élus avec chant de triomphe;
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Et il leur donna les pays des nations, et ils possédèrent le travail des peuples;
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Afin qu’ils gardent ses statuts, et qu’ils observent ses lois. Louez Jah!

< Psalms 105 >