< Psalms 105 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Célébrez Yahweh, invoquez son nom, faites connaître parmi les nations ses grandes œuvres.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Chantez-le, célébrez-le! Proclamez toutes ses merveilles.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Glorifiez-vous de son saint nom; joyeux soit le cœur de ceux qui cherchent Yahweh!
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Cherchez Yahweh et sa force, ne cessez pas de chercher sa face.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Souvenez-vous des merveilles qu’il a opérées, de ses prodiges et des jugements sortis de sa bouche,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
race d’Abraham, son serviteur, enfants de Jacob, ses élus.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Lui, Yahweh, est notre Dieu; ses jugements atteignent toute la terre.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Il se souvient éternellement de son alliance, de la parole qu’il a affirmée pour mille générations,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
de l’alliance qu’il a contractée avec Abraham, et du serment qu’il a fait à Isaac.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Il l’a érigé pour Jacob en loi, pour Israël en alliance éternelle,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
disant: « Je te donnerai le pays de Chanaan comme la part de ton héritage. »
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Comme ils étaient alors en petit nombre, peu nombreux et étrangers dans le pays,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
qu’ils allaient d’une nation à l’autre, et d’un royaume vers un autre peuple,
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
il ne permit à personne de les opprimer, et il châtia les rois à cause d’eux:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
« Ne touchez pas à mes oints, et ne faites pas de mal à mes prophètes! »
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Il appela la famine sur le pays, il les priva du pain qui les soutenait.
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Il envoya devant eux un homme: Joseph fut vendu comme esclave.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
On serra ses pieds dans des liens, on le jeta dans les fers,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
jusqu’au jour où s’accomplit sa prédiction, et où la parole de Dieu le justifia.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Le roi envoya ôter ses liens, le souverain des peuples le mit en liberté.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Il l’établit seigneur sur sa maison, et gouverneur de tous ses domaines,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
afin de lier les princes, selon son gré, et pour enseigner la sagesse à ses anciens.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Alors Israël vint en Égypte, et Jacob séjourna dans le pays de Cham.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Dieu accrut grandement son peuple, et le rendit plus puissant que ses oppresseurs.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Il changea leur cœur, au point qu’ils haïrent son peuple, et usèrent de perfidie envers ses serviteurs.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
Il envoya Moïse, son serviteur, et Aaron qu’il avait choisi.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Ils accomplirent ses prodiges parmi eux, ils firent des miracles dans le pays de Cham.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Il envoya des ténèbres et il fit la nuit, et ils ne furent pas rebelles à sa parole.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Il changea leurs eaux en sang, et fit périr leurs poissons.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Leur pays fourmilla de grenouilles, jusque dans les chambres de leurs rois.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Il dit, et vint une nuée d’insectes, des moucherons sur tout leur territoire.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Il leur donna pour pluie de la grêle, des flammes de feu dans leur pays.
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Il frappa leurs vignes et leurs figuiers, et brisa les arbres de leur contrée.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Il dit, et arriva la sauterelle, des sauterelles sans nombre;
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
elle dévorèrent toute l’herbe de leur pays, elles dévorèrent les produits de leurs champs.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Il frappa tous les premiers-nés de leurs pays, les prémices de toute leur vigueur.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Il fit sortir son peuple avec de l’argent et de l’or, et nul dans ses tribus ne chancela.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Les Égyptiens se réjouirent de leur départ, car la crainte d’Israël les avait saisis.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Il étendit la nuée pour les couvrir, et le feu pour les éclairer la nuit.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
À leur demande, il fit venir des cailles, et il les rassasia du pain du ciel.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Il ouvrit le rocher, et des eaux jaillirent; elles coulèrent comme un fleuve dans le désert.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Car il se souvint de sa parole sainte, d’Abraham, son serviteur.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Il fit sortir son peuple dans l’allégresse, ses élus au milieu des cris de joie.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
Il leur donna les terres des nations, et ils possédèrent le fruit du travail des peuples,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
à la condition de garder ses préceptes, et d’observer ses lois. Alleluia!