< Psalms 105 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Oslavujte Hospodina, ohlašujte jméno jeho, oznamujte mezi národy skutky jeho.
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
Zpívejte jemu, žalmy prozpěvujte jemu, rozmlouvejte o všech divných skutcích jeho.
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
Chlubte se jménem svatým jeho; vesel se srdce těch, kteříž hledají Hospodina.
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
Hledejte Hospodina a síly jeho, hledejte tváři jeho ustavičně.
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
Rozpomínejte se na divné skutky jeho, kteréž činil, na zázraky jeho a na soudy úst jeho,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
Símě Abrahamovo, služebníka jeho, synové Jákobovi, vyvolení jeho.
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
Onť jest Hospodin Bůh náš, na vší zemi soudové jeho.
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
Pamatuje věčně na smlouvu svou, na slovo, kteréž přikázal až do tisíce pokolení,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
Kteréž upevnil s Abrahamem, a na přísahu svou učiněnou Izákovi.
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
Nebo ji utvrdil Jákobovi za ustanovení, Izraelovi za smlouvu věčnou,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
Pravě: Tobě dám zemi Kananejskou za podíl dědictví vašeho,
12 Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
Ješto jich byl malý počet, malý počet, a ještě v ní byli pohostinu.
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
Přecházeli zajisté z národu do národu, a z království k jinému lidu.
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
Nedopustil žádnému ublížiti jim, ano i krále pro ně trestal, řka:
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
Nedotýkejte se pomazaných mých, a prorokům mým nečiňte nic zlého.
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
Když přivolav hlad na zemi, všecku hůl chleba polámal,
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
Poslal před nimi muže znamenitého, jenž za služebníka prodán byl, totiž Jozefa.
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
Jehož nohy sevřeli pouty, železa podniknouti musil,
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
Až do toho času, když se zmínka stala o něm; řeč Hospodinova zkusila ho.
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
Poslav král, propustiti ho rozkázal, panovník lidu svobodna ho učinil.
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
Ustanovil ho pánem domu svého, a panovníkem všeho vládařství svého,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
Aby vládl i knížaty jeho podlé své líbosti, a starce jeho vyučoval moudrosti.
23 Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
Potom všel Izrael do Egypta, a Jákob pohostinu byl v zemi Chamově.
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
Kdež rozmnožil Bůh lid svůj náramně, a učinil, aby silnější byl nad nepřátely své.
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Změnil mysl těchto, aby v nenávisti měli lid jeho, a aby ukládali lest o služebnících jeho.
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
I poslal Mojžíše slouhu svého, a Arona, kteréhož vyvolil.
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
Kteříž předložili jim slova znamení jeho a zázraků v zemi Chamově.
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Poslal tmu, a zatmělo se, aniž odporná byla slovu jeho.
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
Obrátil vody jejich v krev, a zmořil ryby v nich.
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
Vydala země jejich množství žab, i v pokoleních králů jejich.
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
Řekl, i přišla směsice žížal, a stěnice na všecky končiny jejich.
32 Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
Dal místo deště krupobití, oheň hořící na zemi jejich,
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
Tak že potloukl réví jejich i fíkoví jejich, a zpřerážel dříví v krajině jejich.
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
Řekl, i přišly kobylky a chroustů nesčíslné množství.
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
I sežrali všelikou bylinu v krajině jejich, a pojedli úrody země jejich.
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
Nadto pobil všecko prvorozené v zemi jejich, počátek všeliké síly jejich.
37 Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
Tedy vyvedl své s stříbrem a zlatem, aniž byl v pokoleních jejich, ješto by se poklesl.
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
Veselili se Egyptští, když tito vycházeli; nebo byl připadl na ně strach Izraelských.
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
Roztáhl oblak k zastírání jich, a oheň k osvěcování noci.
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
K žádosti přivedl křepelky, a chlebem nebeským sytil je.
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
Otevřel skálu, i tekly vody, a odcházely přes vyprahlá místa jako řeka.
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
Nebo pamětliv byl na slovo svatosti své, k Abrahamovi služebníku svému mluvené.
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
Protož vyvedl lid svůj s radostí, s prozpěvováním vyvolené své.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
A dal jim země pohanů, a tak úsilí národů dědičně obdrželi,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Aby zachovávali ustanovení jeho, a práv jeho ostříhali. Halelujah.

< Psalms 105 >