< Psalms 103 >
1 Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
Av David. Min sjel, lov Herren, og alt som i mig er, love hans hellige navn!
2 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
Min sjel, lov Herren og glem ikke alle hans velgjerninger!
3 ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
Han som forlater all din misgjerning, som læger alle dine sykdommer,
4 ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
han som forløser ditt liv fra graven, som kroner dig med miskunnhet og barmhjertighet,
5 ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
han som metter din sjel med det som godt er, så du blir ung igjen likesom ørnen.
6 Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
Herren gjør rettferd og rett mot alle undertrykte.
7 Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
Han kunngjorde sine veier for Moses, sine gjerninger for Israels barn.
8 Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
Herren er barmhjertig og nådig, langmodig og rik på miskunnhet.
9 Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
Han går ikke alltid i rette og gjemmer ikke på vrede evindelig.
10 Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
Han gjør ikke med oss efter våre synder og gjengjelder oss ikke efter våre misgjerninger.
11 Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
For så høi som himmelen er over jorden, er hans miskunnhet mektig over dem som frykter ham.
12 Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
Så langt som øst er fra vest, lar han våre misgjerninger være langt fra oss.
13 Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
Som en far forbarmer sig over sine barn, forbarmer Herren sig over dem som frykter ham.
14 nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
For han vet hvorledes vi er skapt, han kommer i hu at vi er støv.
15 Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
Et menneskes dager er som gresset; som blomsten på marken, således blomstrer han.
16 afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
Når vinden farer over ham, er han ikke mere, og hans sted kjenner ham ikke mere.
17 Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
Men Herrens miskunnhet er fra evighet og inntil evighet over dem som frykter ham, og hans rettferdighet mot barnebarn,
18 sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
mot dem som holder hans pakt, og dem som kommer hans bud i hu, så de gjør efter dem.
19 Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
Herren har reist sin trone i himmelen, og hans rike hersker over alle ting.
20 Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
Lov Herren, I hans engler, I veldige i makt, som fullbyrder hans ord, idet I adlyder hans ords røst!
21 Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Lov Herren, alle hans hærskarer, I hans tjenere som gjør hans vilje!
22 Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
Lov Herren, alle hans gjerninger, på alle steder hvor han hersker! Min sjel, lov Herren!