< Psalms 103 >
1 Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
De David. Ô mon âme, bénis le Seigneur, et que tout ce qui est en moi bénisse son saint nom.
2 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
Ô mon âme, bénis le Seigneur, et n'oublie aucune de ses louanges.
3 ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
C'est lui qui te remet tes fautes et te guérit de toutes tes infirmités.
4 ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
C'est lui qui rachète ta vie de la corruption, et te couronne en sa miséricorde et sa compassion.
5 ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
C'est lui qui te rassasie de biens au gré de tes désirs; il renouvellera ta jeunesse comme celle de l'aigle.
6 Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
Le Seigneur fait miséricorde et justice aux opprimés.
7 Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
Il a fait connaître ses voies à Moïse, et ses volontés aux fils d'Israël.
8 Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
Le Seigneur est miséricordieux et compatissant, il est longanime et plein de miséricorde.
9 Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
Il ne sera pas irrité sans fin; il ne sera pas éternellement indigné.
10 Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
Il ne nous a point traités selon nos péchés, et il ne nous a point rétribués selon nos iniquités.
11 Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Car autant le ciel est au-dessus de la terre, autant le Seigneur a confirmé sa miséricorde sur ceux qui le craignent.
12 Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
Autant il y a de distance de l'orient à l'occident, autant il a éloigné de nous nos iniquités.
13 Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
Et comme un père a compassion de ses fils, ainsi le Seigneur a compassion de ceux qui le craignent.
14 nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
Il sait de quelle matière nous sommes formés: souviens-toi, Seigneur, que nous sommes poussière!
15 Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
Les jours de l'homme sont comme l'herbe des champs; il fleurira comme la plante sauvage.
16 afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
L'esprit a passé en lui, et il n'est plus, et il ne reconnaîtra plus la place où il était.
17 Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
Mais la miséricorde du Seigneur est de siècles en siècles sur ceux qui le craignent; et sa justice sur les fils de leurs fils,
18 sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
Sur ceux qui gardent son alliance et se souviennent de ses commandements.
19 Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
Le Seigneur a préparé son siège dans le ciel, et de son trône il domine sur toutes choses.
20 Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
Bénissez le Seigneur, vous tous qui êtes ses anges, pleins de force, prompts à exécuter sa parole, à obéir à la voix de ses discours.
21 Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Bénissez le Seigneur, tous qui êtes ses armées, vous qui êtes les ministres de ses volontés.
22 Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
Bénissez le Seigneur, vous qui êtes tous ses œuvres; en tous les lieux où il règne, ô mon âme, bénis le Seigneur!