< Psalms 103 >

1 Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
[A Psalm] of David. Bless Jehovah, O my soul; and all that is within me, [bless] his holy name!
2 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
Bless Jehovah, O my soul, and forget not all his benefits:
3 ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
Who forgiveth all thine iniquities, who healeth all thy diseases;
4 ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
Who redeemeth thy life from the pit, who crowneth thee with loving-kindness and tender mercies;
5 ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
Who satisfieth thine old age with good [things]; thy youth is renewed like the eagle's.
6 Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
Jehovah executeth righteousness and justice for all that are oppressed.
7 Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
He made known his ways unto Moses, his acts unto the children of Israel.
8 Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
Jehovah is merciful and gracious, slow to anger, and abundant in loving-kindness.
9 Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
He will not always chide, neither will he keep [his anger] for ever.
10 Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
He hath not dealt with us according to our sins, nor rewarded us according to our iniquities.
11 Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
For as the heavens are high above the earth, so great is his loving-kindness toward them that fear him.
12 Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
As far as the east is from the west, so far hath he removed our transgressions from us.
13 Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
As a father pitieth [his] children, so Jehovah pitieth them that fear him.
14 nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
For himself knoweth our frame; he remembereth that we are dust.
15 Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
As for man, his days are as grass; as a flower of the field, so he flourisheth:
16 afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
For the wind passeth over it, and it is gone, and the place thereof knoweth it no more.
17 Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
But the loving-kindness of Jehovah is from everlasting and to everlasting, upon them that fear him, and his righteousness unto children's children,
18 sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
To such as keep his covenant and to those that remember his precepts to do them.
19 Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
Jehovah hath established his throne in the heavens, and his kingdom ruleth over all.
20 Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
Bless Jehovah, ye his angels, mighty in strength, that execute his word, hearkening unto the voice of his word.
21 Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
Bless Jehovah, all ye his hosts; ye ministers of his that do his will.
22 Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
Bless Jehovah, all his works, in all places of his dominion. Bless Jehovah, O my soul!

< Psalms 103 >