< Psalms 102 >

1 Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
Molitev za ubozega, ko je v stiski in pred Gospoda izliva premišljevanje svoje. Gospod, čuj molitev mojo, in vpitje moje pridi do tebe.
2 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
Ne skrivaj mi obličja svojega, ko sem v stiski; nagni mi uho svoje, ko kličem; naglo me usliši.
3 Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
Ker ginejo kakor dim dnevi moji; in kosti moje se sušé kakor pogorišče.
4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
Zadeto vene kakor trava srce moje, ker pozabljam použivati svojo jed.
5 Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
Od glasú zdihovanja mojega drži se kost moja mojega mesa.
6 Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
Podoben sem pelikanu v puščavi; kakor sova sem v podrtinah.
7 Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
Vedno sem podoben samotnemu vrabcu na strehi.
8 Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
Ves dan me sramoté sovražniki moji; zoper mene divjajoč prisezajo pri meni.
9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
Ker pepel jem kakor kruh; in pijače svoje mešam z jokom.
10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
Zaradi nevolje tvoje in srdite jeze tvoje; ker vzdignil si me in vrgel me na tla.
11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
Dnevi moji so podobni senci, ki se je nagnila; in jaz sem se posušil kakor trava.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
Ti pa, Gospod, ostajaš vekomaj, in spomin tvoj od roda do roda.
13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
Ti bodeš vstal in usmilil se Sijona, ker čas je storiti mu milost, ker prišel je čas določeni,
14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
Ko se naj hlapci tvoji veselé njegovega kamenja, in milost storé njegovemu prahu;
15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
Da česté narodi ime Gospodovo, in vsi kralji zemlje čast tvojo.
16 Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
Ko bode Gospod zidal Sijon in prikazal se v časti svoji,
17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
Ozrl se bode v nazega molitev, in ne bode zametal njih molitve.
18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
Zapiše se naj to naslednjemu rodu, da ljudstvo poživljeno hvali Gospoda.
19 “Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
Ker pogledal bode z višave svetosti svoje Gospod, ozrl se z nebés na zemljo.
20 láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
Da usliši jetnika zdihovanje, da oprosti njé, ki se že izdajajo smrti;
21 Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
Da oznanjajo na Sijonu ime Gospodovo, in hvalo njegovo v Jeruzalemu,
22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
Ko se zbirajo ljudstva in kralji čestit Gospoda.
23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
Pobija sicer na tem poti moči moje, dnî moje krajša,
24 Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
Ali govorim: Bog moj mogočni, ne vzemi me v sredi mojih dnî; skozi vse rodove so dnevi tvoji,
25 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Predno si ustanovil zemljo, in so bila nebesa delo tvojih rok;
26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
Tisto bode prešlo, ti pa ostaneš; tisto, pravim, vse postara se kakor oblačilo; kakor obleko jih izpremeniš in izpremené se.
27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
Ti pa si isti, in let tvojih ni konca.
28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”
Sinovi hlapcev tvojih bodo prebivali, in njih seme se utrdi pred teboj.

< Psalms 102 >