< Psalms 102 >

1 Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
Modlitwa strapionego, gdy uciśniony wylewa przed PANEM swoją skargę. PANIE, wysłuchaj mojej modlitwy i niech przyjdzie do ciebie moje wołanie.
2 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
Nie ukrywaj przede mną swego oblicza, w dniu mego ucisku nakłoń ku mnie swego ucha; w dniu, w którym cię wzywam, szybko mnie wysłuchaj.
3 Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
Moje dni bowiem nikną jak dym, a moje kości są rozpalone jak ognisko.
4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
Moje serce jest porażone i usycha jak trawa, [tak] że zapomniałem jeść chleb.
5 Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
Od głosu mego wołania moje kości przylgnęły mi do ciała.
6 Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
Jestem podobny do pelikana na pustyni, jestem jak sowa na pustkowiu.
7 Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
Czuwam i jestem jak samotny wróbel na dachu.
8 Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
Przez cały dzień znieważają mnie moi wrogowie i przeklinają mnie ci, którzy szaleją przeciwko mnie.
9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
Jadam bowiem popiół jak chleb, a mój napój mieszam ze łzami;
10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
Z powodu twego gniewu i zapalczywości, bo podniosłeś mnie i strąciłeś.
11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
Moje dni są jak chylący się cień, a ja usycham jak trawa.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
Ale ty, PANIE, trwasz na wieki, a twoja pamięć z pokolenia na pokolenie.
13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
Powstaniesz i zmiłujesz się nad Syjonem, bo czas, byś się nad nim zlitował, gdyż nadszedł czas wyznaczony.
14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
Twoi słudzy bowiem miłują jego kamienie i litują się nad jego prochem;
15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
A poganie będą się bać imienia PANA i wszyscy królowie ziemi – twojej chwały;
16 Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
Gdy PAN odbuduje Syjon i ukaże się w swojej chwale;
17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
Przychyli się do modlitwy opuszczonych i nie pogardzi ich modlitwą.
18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
Zapiszą to dla przyszłego pokolenia, a lud, który ma być stworzony, będzie chwalić PANA.
19 “Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
Spojrzał bowiem z wysokości swojej świątyni; PAN popatrzył z nieba na ziemię;
20 láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
Aby wysłuchać jęku więźniów i uwolnić skazanych na śmierć;
21 Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
Aby głosili na Syjonie imię PANA i jego chwałę w Jeruzalem;
22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
Gdy się zgromadzą razem narody i królestwa, aby służyć PANU.
23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
Osłabił w drodze moją siłę, skrócił moje dni.
24 Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
Powiedziałem: Mój Boże, nie zabieraj mnie w połowie moich dni; twoje lata bowiem [trwają] z pokolenia na pokolenie.
25 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Ty dawno założyłeś [fundamenty] ziemi i niebiosa są dziełem twoich rąk.
26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
One przeminą, ale ty pozostajesz; wszystkie jak szata się zestarzeją, zmienisz je jak płaszcz i będą odmienione.
27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
Ale ty [zawsze jesteś] ten sam, a twoje lata nigdy się nie skończą.
28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”
Synowie twoich sług będą trwać [u ciebie], a ich potomstwo zostanie przed tobą utwierdzone.

< Psalms 102 >