< Psalms 102 >

1 Àdúrà olùpọ́njú tí àárẹ̀ mú, tí ó sí ọkàn rẹ̀ payá níwájú Olúwa. Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, jẹ́ kí igbe ẹ̀bẹ̀ mi kí ó wá sí ọ̀dọ̀ rẹ.
Prière de l'affligé, lorsqu'il est abattu et qu'il exhale sa plainte devant l'Éternel. Éternel, écoute ma prière, Et que mon cri parvienne jusqu'à toi!,
2 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi ní ọjọ́ tí èmi wà nínú ìpọ́njú. Dẹ etí rẹ sí mi; nígbà tí mo bá pè, dá mi lóhùn kíákíá.
Ne me cache pas ta face, au jour de ma détresse; Incline vers moi ton oreille! Au jour où je t'invoque, hâte-toi de me répondre!
3 Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín; egungun mi sì jóná bí ààrò.
Car mes jours s'évanouissent comme une fumée, Et mes os se consument comme un brasier.
4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko; mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
Mon coeur a été frappé, et il se dessèche comme l'herbe; J'oublie même de manger mon pain.
5 Nítorí ohùn ìkérora mi, egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran-ara mi.
Je pousse de tels gémissements. Que mes os s'attachent à ma chair.
6 Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù: èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
Je ressemble au pélican du désert; Je suis comme le hibou des ruines.
7 Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
Je n'ai plus de sommeil, Et je suis comme le passereau solitaire sur un toit.
8 Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí; àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
Tous les jours, mes ennemis m'outragent. Et mes adversaires en fureur prononcent mon nom Comme un nom maudit.
9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
Je fais de la cendre ma nourriture. Et je mêle des larmes à mon breuvage,
10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
A cause de ton indignation et de ton courroux; Car tu m'as saisi et rejeté au loin.
11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́ èmi sì rọ bí koríko.
Mes jours s'inclinent comme l'ombre du soir Et je me dessèche comme l'herbe.
12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé; ìrántí rẹ láti ìran dé ìran.
Mais toi, ô Éternel, tu règnes à perpétuité. Et ta mémoire subsiste d'âge en âge.
13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni, nítorí ìgbà àti ṣe ojúrere sí i; àkókò náà ti dé.
Tu te lèveras, tu auras pitié de Sion. Il est temps de lui faire grâce: L'heure est venue!
14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ; wọ́n sì káàánú erùpẹ̀ rẹ.
Car tes serviteurs en chérissent les pierres; Ils aiment jusqu'à sa poussière.
15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, gbogbo ọba ayé yóò máa bẹ̀rù ògo rẹ.
Alors les peuples craindront le nom de l'Éternel. Tous les rois de la terre, ô Dieu, verront ta gloire,
16 Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
Parce que l'Éternel aura rebâti Sion, Qu'il aura paru dans sa gloire,
17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní; kì yóò sì gan ẹ̀bẹ̀ wọn.
Qu'il aura écouté la requête des misérables, Et n'aura pas méprisé leur supplication.
18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀, àwọn ènìyàn tí a kò tí ì dá yóò yin Olúwa:
Cela sera écrit pour la génération future. Et le peuple qui sera créé, louera l'Éternel.
19 “Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀run wá ni ó bojú wo ayé,
Car l'Éternel abaissera ses regards, Du haut de sa demeure sainte. Et, du haut des cieux, l'Éternel jettera les yeux sur la terre,
20 láti gbọ́ ìrora ará túbú, láti tú àwọn tí a yàn sí ikú sílẹ̀.”
Pour écouter les gémissements du captif, Pour délivrer ceux qui sont voués à la mort.
21 Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni àti ìyìn rẹ̀ ní Jerusalẹmu.
Alors on célébrera le nom de l'Éternel dans Sion, Et ses louanges dans Jérusalem,
22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti ìjọba pọ̀ láti máa sìn Olúwa.
Quand tous les peuples, ainsi que les royaumes, Se rassembleront pour servir l'Eternel.
23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀, ó gé ọjọ́ mi kúrú.
Dieu a brisé ma force au milieu de ma course; Il a abrégé mes jours.
24 Èmi sì wí pé: “Ọlọ́run mi, má ṣe mú mi kúrò ní agbede-méjì ọjọ́ mi; ọdún rẹ̀ ń lọ láti ìran dé ìran.
J'ai dit: mon Dieu, ne m'enlève pas à la fleur de l'âge, Toi dont les années subsistent de siècle en siècle!
25 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Tu as jadis fondé la terre, Et les cieux sont l'oeuvre de tes mains.
26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà; gbogbo wọn ni yóò gbó bí aṣọ. Bí ẹ̀wù ni ìwọ yóò pààrọ̀ wọn wọn yóò sì di àpatì.
Ils périront; mais toi, tu subsisteras. Ils s'useront tous comme un vêtement; Tu les changeras comme un habit, et ils passeront.
27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀, ọdún rẹ kò sì ní òpin.
Mais toi, tu es toujours le même. Et tes années ne finiront point.
28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́; a ó sì fi ẹsẹ̀ irú-ọmọ wọn sọlẹ̀ ní iwájú rẹ.”
Les enfants de tes serviteurs auront une demeure assurée, Et leur postérité se perpétuera sous tes yeux.

< Psalms 102 >