< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
En Psalm Davids. Om nåd och rätt vill jag sjunga; och dig, Herre, lofsäga.
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Jag handlar försigteliga och redeliga med dem som mig tillhöra, och vandrar troliga i mitt hus.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Jag tager mig ingen ond sak före; jag hatar öfverträdaren, och låter honom icke när mig blifva.
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Ett vrångt hjerta måste vika ifrå mig; den onda lider jag icke.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Den sin nästa hemliga baktalar, honom förgör jag; den der storlåtig är och högt sinne hafver, honom lider jag icke.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Mine ögon se efter de trogna i landena, att de måga när mig bo; och hafver gerna fromma tjenare.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Falskt folk håller jag icke i mitt hus; ljugare trifvas icke när mig.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Bittida förgör jag alla ogudaktiga i landena, att jag må utrota alla ogerningsmän utu Herrans stad.

< Psalms 101 >