< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
Psalm samego Dawida. O miłosierdziu i o sądzie śpiewać będę; tobie, o Panie! śpiewać będę.
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Ostrożnym będę na drodze uprzejmej, kiedy przyjdziesz do mnie; będę chodził ustawicznie w szczerości serca mego, w domu moim.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Nie położę przed oczy moje złej rzeczy; każdą sprawę występników mam w nienawiści, a nie chwyci się mnie.
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Serce przewrotne odstąpi odemnie, a o złe nie będę dbał.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Tego, który potajemnie obmawia bliźniego swego, wytnę; oczów wyniosłych, i serca nadętego nie będę mógł cierpieć.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Oczy moje obrócone będą na prawdomównych w ziemi, aby siadali zemną; kto chodzi drogą uprzejmą, ten mi służyć będzie.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Nie będzie mieszkał w domu moim zdrajca, ten, który mówi kłamstwo, nie ostoi się przed oczyma memi.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Co poranek tracić będę wszystkich niezbożnych na ziemi, abym tak wykorzenił z miasta Pańskiego wszystkich, którzy czynią nieprawość.

< Psalms 101 >