< Psalms 101 >
1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
Un Psaume de David. Seigneur, je chanterai ta miséricorde et ton jugement; je chanterai un psaume,
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Et je marcherai avec intelligence dans la voie sans tache; quand viendras-tu à moi? J'ai marché au milieu de ma maison, dans l'innocence de mon cœur.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Je n'ai mis aucune œuvre mauvaise devant mes yeux; j'ai haï les prévaricateurs. Je ne me suis point attaché
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Au cœur dépravé; et le méchant se détournant de moi, je ne l'ai point connu.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Celui qui venait en secret déchirer son prochain, je l'ai toujours poursuivi. Je n'ai point mangé avec des gens à l'œil superbe, au cœur insatiable.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Mes yeux s'arrêtent sur les fidèles de la terre, pour les faire asseoir avec moi; celui qui chemine dans la voie sans tache était mon ministre.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Le superbe n'a point séjourné en ma demeure; le prieur injuste n'a point réussi devant mes yeux.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Le matin, je mettais à mort tous les pécheurs de la terre, afin d'exterminer dans la ville du Seigneur les ouvriers d'iniquité.