< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
Psaume de David Je veux chanter la bonté et la justice; C’est toi, Yahweh, que je veux célébrer.
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Je prendrai garde à la voie de l’innocence. — Quand viendras-tu à moi? — Je marcherai dans l’intégrité de mon cœur, au milieu de ma maison.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Je ne mettrai devant mes yeux aucune action mauvaise. Je hais la conduite perverse; elle ne s’attachera pas à moi.
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Un cœur faux ne sera jamais le mien; je ne veux pas connaître le mal.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Le détracteur qui déchire en secret son prochain, je l’exterminerai; L’homme au regard hautain et au cœur gonflé d’orgueil, je ne le supporterai pas.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
J’aurai les yeux sur les hommes fidèles du pays, pour qu’ils demeurent auprès de moi; celui qui marche dans une voie intègre sera mon serviteur.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Il n’aura pas de place dans ma maison, celui qui agit avec fourberie; celui qui profère le mensonge ne subsistera pas devant mes yeux.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Chaque matin j’exterminerai tous les méchants du pays, afin de retrancher de la cité de Yahweh tous ceux qui commettent l’iniquité.

< Psalms 101 >