< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
David’s. A Melody. Of lovingkindness and of justice, will I sing! Unto thee, O Yahweh, will I touch the strings!
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
I will behave myself wisely in a blameless way, When wilt thou come in unto me? I will walk to and fro in the blamelessness of my heart, —in the midst of my house:
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
I will not set before mine eyes, a vile thing, —The doing of them who fall away, I hate, It shall not cleave unto me;
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
A perverse heart, shall depart from me, A maker of mischief, will I not acknowledge;
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
He that uttereth slander in secret against his friend, him, will I root out; One of lofty eyes, and of an ambitious heart, him shall I not be able to endure.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Mine eyes, shall be upon the faithful of the land, That they may dwell with me, —he that walketh in a blameless way, he, shall attend me.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
There shall not dwell in the midst of my house, One who worketh deceit, —he that speaketh falsehoods, shall not be established before mine eyes;
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Morning by morning, will I uproot, All the lawless ones of the land, That I may cut off, out of the city of Yahweh—All the workers of iniquity.

< Psalms 101 >