< Psalms 101 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Èmi yóò kọrin ìfẹ́ àti òdodo; sí ọ Olúwa, èmi yóò máa kọrin ìyìn.
Žalm Davidův. O milosrdenství a soudu zpívati budu, tobě, ó Hospodine, žalmy budu zpívati.
2 Èmi yóò máa rin ìrìn mi pẹ̀lú ọgbọ́n láìlẹ́ṣẹ̀, ìgbà wo ni ìwọ yóò wá sí ọ̀dọ̀ mi? Èmi yóò máa rìn ní ilé mi pẹ̀lú àyà pípé.
Opatrně se míti budu na cestě přímé, až přijdeš ke mně; choditi budu ustavičně v upřímnosti srdce svého i v domě svém.
3 Èmi kì yóò gbé ohun búburú sí iwájú mi: iṣẹ́ àwọn tí ó yapa ni èmi kórìíra. Wọn kì yóò rọ̀ mọ́ mi.
Nepředstavímť sobě před oči věci nešlechetné; skutek uchylujících se v nenávisti mám, nepřichytíť se mne.
4 Agídí ọkàn yóò kúrò lọ́dọ̀ mi; èmi kì yóò mọ ènìyàn búburú.
Srdce převrácené odstoupí ode mne, zlého nebudu oblibovati.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń sọ̀rọ̀ ẹnìkejì rẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀, òun ní èmi yóò gé kúrò ẹni tí ó bá gbé ojú rẹ̀ ga tí ó sì ní ìgbéraga àyà, òun ní èmi kì yóò faradà fún.
Škodícího jazykem bližnímu svému tajně, tohoť vytnu; očí vysokých a mysli naduté nikoli nebudu moci trpěti.
6 Ojú mi yóò wà lára àwọn olóòtítọ́ lórí ilẹ̀, kí wọn kí ó lè máa bá mi gbé; ẹni tí ó bá n rin ọ̀nà pípé òun ni yóò máa sìn mí.
Oči mé na pravdomluvné v zemi, aby sedali se mnou; kdož chodí po cestě upřímé, tenť mi sloužiti bude.
7 Ẹni tí ó bá ń ṣe ẹ̀tàn, kì yóò gbé ilé mi, kò sí ẹni tí ń ṣèké tí yóò dúró ní iwájú mi.
Nebude bydliti v domě mém činící lest, a mluvící lež nebude míti místa u mne.
8 Ní ojoojúmọ́ ní èmi yóò wá máa pa a lẹ́nu mọ gbogbo àwọn ènìyàn búburú ilẹ̀ náà; èmi yóò gé àwọn olùṣe búburú kúrò ní ìlú Olúwa.
Každého jitra pléniti budu všecky nešlechetné z země, abych tak vyplénil z města Hospodinova všecky, kdož páší nepravost.

< Psalms 101 >