< Psalms 100 >

1 Saamu. Fún ọpẹ́. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Olúwa, gbogbo ayé.
Everyone in the world should shout joyfully to Yahweh!
2 Ẹ fi ayọ̀ sin Olúwa, ẹ wá síwájú rẹ̀ pẹ̀lú orin dídùn
We should worship Yahweh gladly! We should come before him singing joyful songs.
3 Olúwa Ọlọ́run ni ó dá wa, kí ẹ̀yin kí ó mọ̀ pé tirẹ̀ ni àwa, àwa ní ènìyàn rẹ̀ àti àgùntàn pápá rẹ̀.
We should acknowledge/recognize that Yahweh is God; it is he who made us, [so] we belong to him. We are the people that he takes care of [MET]; we are [like] sheep that are cared for by their shepherd.
4 Ẹ lọ sí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ àti sí àgbàlá rẹ̀ pẹ̀lú ìyìn; ẹ fi ọpẹ́ àti ìyìn fún orúkọ rẹ̀.
Enter the gates [of his temple] thanking him; enter the courtyard [of the temple] singing songs to praise him! Thank him and praise him,
5 Nítorí tí Olúwa pọ̀ ní oore ìfẹ́ rẹ̀ sì wà títí láé; àti òtítọ́ rẹ̀ láti ìran de ìran.
because Yahweh always [does] good [things for us]. He faithfully loves us, and (is faithful/is loyal to us forever/will never forsake us).

< Psalms 100 >