< Psalms 10 >
1 Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré? Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?
Aw Bawipa, kawtih ak hla na nang dyih? Kyinaak a awm huiawh kawtih nang thuh qu valh?
2 Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera, ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.
Ak oek qu soeih thlak che ing tha amak awm thlangkhqi, amah ing teng nawh am tu thlangkhqi ce hquut hy.
3 Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀; Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa.
Ak kawlung hymnaak awh oek qu nawh; ak lawn na ak ngaih ce zoeksang nawh Bawipa taw hlah phlam hy.
4 Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀; kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.
Ak oek qu thlak che ingtaw amah ingkaw amah am sui qu nawh; Ak poeknaak boeih awh Khawsa ham hun qoe am awm hy.
5 Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo; òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i; òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.
A lamkhqi boeih awh a zo awm hy. Anaa a hqam aih awh nang a cawngpyinaak awi ing hla qu hy nih; a qaalkhqi boeih ce huhsitnaak ing qaih na hy.
6 O wí fún ara rẹ̀, “Kò sí ohun tí ó lè mì mí. Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà.”
Amah ingtaw, Ikaw ingawm am ning tah sak tikaw; zeel loet nyng saw kyinaak am hu tang tikawng” tinawh poek hy.
7 Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ; wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.
Anih am kha taw seet lawhnaak, qaainaak ingkaw kqih am hqinnaak ing be hy, am lai awh awm kyinaak ingkaw seetnaak doek khoeih ni.
8 Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò. Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀. Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.
Khawkeng imceng khqi awh ngawi nawh, ak awm poek poek khqi ce mam nawh him hy.
9 Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí; Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́; ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.
Sendeih ing ak kawk khui awhkawng a qeh dym amyihna, a hlip naak awh qeh hy, hulkung amak awm thlang ce tu aham qeh nawh; bawmkung amak awmkhqi ce lawk ing sing hy.
10 Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀; kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.
A thekhanaak thlangkhqi ce kqih am hqin hy; cekkhqi ce ak thaawmnaak khuiawh tlaak sak khqi hy.
11 Ó wí fún ara rẹ̀, “Ọlọ́run ti gbàgbé; Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé.”
Amah ingtaw Khawsa ing hilh hawh hy; a hai sing khoep nawh am hu thai voel hy” tina poek hy.
12 Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run. Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.
Aw Bawipa, tho hlah! Aw Khawsa na kut thlek hlah, hulkung amak ta thlangkhqi ce koeh hilh.
13 Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run? Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀, “Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò”?
Thlak che ing kawtih Bawipa a thekha naak? Ikawtih amah ingkaw amah, “Ikaw am ni tina tang”, tina ak poek hy voei?
14 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora; Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ. Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ; Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.
Cehlai aw Khawsa, kyinaak ingkaw ko kqangnaak ve toek nawhtaw; na kut khuiawh lawh aham poek lah. Kyinaak ak hukhqi ing nang a venawh pe qu unawh, pa amak takhqi ak hulkung na awm hyk ti.
15 Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi; pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀ tí a kò le è rí.
Thlak chekhqi ingkaw thlak thawlh a baan ce hqem pe nawh; huh thai na ama awm hlan dy awh a thawlhnaak ce tlet pe lah.
16 Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé; àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.
Bawipa taw kumqui awhkawng kumqui dy sangpahrang na awm hy; pilnam thlangkhqi taw a kut awhkawng kqeng bang kawm uh.
17 Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára; Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,
Aw Bawipa, khuikha ak hukhqi a ngaihnaak ce zaak penawh; tha na peek coengawh, cekkhqi ang kqangnaak awi ce ngai pe hyk ti.
18 láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára, kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé, kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.
Pa amak takhqi ingkaw a thenaak khqi ce dyih pyi nawh, khawmdek thlangkhqi ing cekkhqi ce am huhsit hqa voel hy.