< Psalms 1 >

1 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà, tí kò rìn ní ìmọ̀ àwọn ènìyàn búburú, ti kò dúró ní ọ̀nà àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, tàbí tí kò sì jókòó ní ibùjókòó àwọn ẹlẹ́gàn.
خوشا به حال کسی که در راه بدکاران قدم نمی‌زند و در راه گناهکاران نمی‌ایستد و با کسانی که خدا را مسخره می‌کنند نمی‌نشیند،
2 Ṣùgbọ́n ayọ̀ inú rẹ̀ wà nínú òfin Olúwa àti nínú òfin rẹ̀ ni ó ń ṣe àṣàrò ní ọ̀sán àti òru.
بلکه مشتاقانه از دستورهای خداوند پیروی می‌کند و شب و روز در آنها تفکر می‌نماید.
3 Ó dàbí igi tí a gbìn sí etí odò tí ń sàn, tí ń so èso rẹ̀ jáde ní àkókò rẹ̀ tí ewé rẹ̀ kì yóò rẹ̀. Ohunkóhun tí ó dáwọ́lé, ni yóò máa yọrí sí rere.
او همچون درختی است که در کنار نهرهای آب کاشته شده و به موقع میوه می‌دهد و برگهایش هرگز پژمرده نمی‌شوند؛ کارهای او همیشه ثمربخش‌اند.
4 Kò le rí bẹ́ẹ̀ fún àwọn ènìyàn búburú! Wọn yóò dàbí ìyàngbò ọkà tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ dànù.
اما بدکاران چنین نیستند. آنها مانند کاهی هستند که در برابر باد پراکنده می‌شود.
5 Nítorí náà àwọn ènìyàn búburú kì yóò le è dìde dúró ní ìdájọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ kì yóò le è dúró ní àwùjọ àwọn olódodo.
آنها در برابر مسند داوری خدا محکوم خواهند شد و به جماعت خداشناسان راه نخواهند یافت.
6 Nítorí Olúwa ń ṣọ́ ọ̀nà àwọn olódodo, ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.
درستکاران توسط خداوند محافظت و هدایت می‌شوند، اما بدکاران به سوی نابودی پیش می‌روند.

< Psalms 1 >