< Proverbs 9 >
1 Ọgbọ́n ti kọ́ ilé rẹ̀, ó ti gbẹ́ òpó o rẹ̀ méjèèjì,
La sabiduría edificó su casa; labró sus siete columnas:
2 ó ti fi ilé pọn tí, ó ti fọ̀nà rokà. Ó sì ti ṣètò o tábìlì oúnjẹ rẹ̀
Mató a su víctima, templó su vino, y puso su mesa.
3 ó ti rán àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ jáde, ó sì ń pè, láti ibi tí ó ga jù láàrín ìlú.
Envió sus criadas, clamó sobre lo más alto de la ciudad:
4 “Jẹ́ kí gbogbo àwọn aláìgbọ́n wọ ibí wá!” Ó ń wí fún àwọn tí kò lọ́gbọ́n pé,
Cualquiera simple, venga acá. A los faltos de entendimiento dijo:
5 “Wá, ẹ wá jẹ́ oúnjẹ mi sì mu wáìnì tí mo ti pò.
Veníd, coméd mi pan; y bebéd del vino que yo he templado.
6 Fi ìwà àìmọ̀kan rẹ sílẹ̀ ìwọ yóò sì yè; rìn ní ọ̀nà òye.
Dejád las simplezas, y vivíd; y andád por el camino de la inteligencia.
7 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹlẹ́gàn wí, kọ lẹ́tà sí àbùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá bá ẹni búburú wí kọ lẹ́tà sí èébú.
El que castiga al burlador, afrenta toma para sí; y el que reprende al impío, su mancha.
8 Má ṣe bá ẹlẹ́gàn wí, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò kórìíra rẹ. Bá ọlọ́gbọ́n wí yóò sì fẹ́ràn rẹ;
No castigues al burlador, porque no te aborrezca: castiga al sabio, y amarte ha.
9 kọ́ ọlọ́gbọ́n ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì gbọ́n sí i kọ́ olódodo ènìyàn lẹ́kọ̀ọ́, yóò sì fi kún ìmọ̀ rẹ̀.
Da instrucción al sabio, y será más sabio: enseña al justo, y añadirá enseñamiento.
10 “Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ nípa Ẹni Mímọ́ ni òye.
El temor de Jehová es el principio de la sabiduría; y la ciencia de los santos es inteligencia.
11 Nítorí nípasẹ̀ mi ọjọ́ rẹ yóò gùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún yóò sì kún ọjọ́ ayé rẹ.
Porque por mí se aumentarán tus días; y años de vida se te añadirán.
12 Bí ìwọ bá gbọ́n, ọgbọ́n rẹ yóò fún ọ ní èrè: bí ìwọ bá jẹ́ ẹlẹ́gàn, ìwọ nìkan ni yóò jìyà.”
Si fueres sabio, para ti lo serás; mas si fueres burlador, tú solo pagarás.
13 Òmùgọ̀ obìnrin jẹ́ aláriwo; ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláìní ìmọ̀.
La mujer insensata es alborotadora, es simple, y no sabe nada:
14 Ó jókòó ní ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀ lórí ìjókòó níbi tí ó ga jù láàrín ìlú,
Asiéntase sobre una silla a la puerta de su casa, en lo alto de la ciudad;
15 ó ń pe àwọn tí ó ń kọjá lọ, tí wọn ń lọ tààrà ní ọ̀nà wọn.
Para llamar a los que pasan por el camino: que van por sus caminos derechos:
16 “Jẹ́ kí gbogbo ẹni tí ó jẹ́ aláìlóye súnmọ́ bí!” Ni ó wí fún ẹni tí òye kù díẹ̀ ká à tó fún.
Cualquiera simple, venga acá. A los faltos de entendimiento, dijo:
17 “Omi tí a jí mu dùn oúnjẹ tí a jẹ ní ìkọ̀kọ̀ a máa ládùn!”
Las aguas hurtadas son dulces; y el pan encubierto es suave.
18 Ṣùgbọ́n wọn ò funra pé àwọn òkú wà níbẹ̀, pé àwọn àlejò rẹ̀ wà ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ isà òkú. (Sheol )
Y no saben, que allí están los muertos; y sus convidados están en los profundos de la sepultura. (Sheol )